Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ọ̀pọ̀ lára àwọn Júù tó ń gbé ní Jerúsálẹ́mù ló gbédè Gíríìkì. Bí àpẹẹrẹ, “àwọn ọkùnrin kan dìde lára àwọn tí wọ́n wá láti inú èyí tí àwọn ènìyàn ń pè ní Sínágọ́gù Àwọn Olómìnira, àti lára àwọn ará Kírénè àti àwọn ará Alẹkisáńdíríà àti lára àwọn tí wọ́n wá láti Sìlíṣíà àti Éṣíà,” ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé èdè Gíríìkì ni wọ́n ń sọ.—Ìṣe 6:1, 9.