Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bíbélì Septuagint sọ pé Jónà hanrun, ìyẹn sì jẹ́ ká mọ bó ṣe sùn wọra tó. Àmọ́, kò ní dáa tá a bá rò pé torí kí Jónà má bàa dá sí nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ ló ṣe lọ wábi sùn sí, a lè rántí pé nígbà míì oorun máa ń kun àwọn tó bá rẹ̀wẹ̀sì. Nígbà tí Jésù wà lọ́gbà Gẹtisémánì lákòókò tí nǹkan ò rọrùn fún un, ńṣe ni Pétérù, Jákọ́bù àti Jòhánù “ń tòògbé nítorí ẹ̀dùn-ọkàn.”—Lúùkù 22:45.