Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Lẹ́sẹ̀ kan náà, Dáfídì dà bí àgùntàn tó fọkàn tán olùṣọ́ rẹ̀. Ojú Jèhófà Olùṣọ́ Àgùntàn Àgbà ló ń wò pé kó máa dáàbò bo òun kó sì máa tọ́ òun sọ́nà. Ìgbẹ́kẹ̀lé pátápátá tó ní nínú Jèhófà ló fi sọ gbólóhùn yìí pé: “Jèhófà ni Olùṣọ́ Àgùntàn mi. Èmi kì yóò ṣaláìní nǹkan kan.” (Sm. 23:1) Jòhánù Olùbatisí pe Jésù ní “Ọ̀dọ́ Àgùntàn Ọlọ́run.”—Jòh. 1:29.