Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ó ṣeé ṣe kí Dáfídì máa rò ó pé dídáàbò bo àwọn onílẹ̀ àti agbo ẹran wọn jẹ́ iṣẹ́ ìsìn kan sí Jèhófà Ọlọ́run. Nígbà yẹn, ohun tí Jèhófà fẹ́ ni pé káwọn àtọmọdọ́mọ Ábúráhámù, Ísákì àti Jékọ́bù máa gbé nílẹ̀ náà. Torí náà, dídáàbò bo ilẹ̀ yẹn lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àtàwọn olè jẹ́ ìjọsìn mímọ́.