Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nǹkan bí ẹgbẹ̀rún méje [7,000] ìgbà ni orúkọ náà, Jèhófà, fara hàn nínú ọ̀rọ̀ Bíbélì ìpilẹ̀ṣẹ̀. Ìtumọ̀ orúkọ náà ni, “Èmi yóò jẹ́ ohun tí èmi yóò jẹ̀.” (Ẹ́kísódù 3:14) Ọlọ́run lè di ohunkóhun tó bá fẹ́ kó bàa lè mú ìfẹ́ rẹ̀ ṣẹ. Orúkọ yìí mú un dáni lójú pé Ọlọ́run kò lè purọ́ àti pé gbogbo ohun tó bá ṣèlérí ló máa ṣẹ.