Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ìwé Mátíù sọ pé àwọn àjèjì náà “ṣí àwọn ìṣúra wọn,” wọ́n sì fún Jésù ní wúrà, oje igi tùràrí àti òjíá. Kẹ́ ẹ sì wá wò ó, ó ṣeé ṣe kí àwọn ẹ̀bùn olówó iyebíye yẹn bọ́ sákòókò gan-an, nítorí pé ó máa tó di dandan fún ìdílé Jésù tí kò fi bẹ́ẹ̀ rí já jẹ láti sá kúrò nílùú.—Mátíù 2:11-15.