Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Ìtàn yìí jẹ́ ká mọ ìwà àìlọ́wọ̀ méjì tí wọ́n hù. Àkọ́kọ́ ni pé, Òfin sọ ní pàtó ohun tó jẹ́ ẹ̀tọ́ àwọn àlùfáà lára ọrẹ ẹbọ. (Diutarónómì 18:3) Àmọ́ ní àgọ́ ìjọsìn náà, àwọn àlùfáà burúkú ti bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe ohun tó yàtọ̀. Ńṣe ni wọ́n máa ń sọ fún àwọn ìránṣẹ́ wọn pé kí wọ́n ki àmúga bọ ẹran tó ń hó lọ́wọ́ nínú ìkòkò, tí wọ́n á sì mú èyí tí ó bá gbé jáde! Ohun kejì ni pé, nígbà táwọn èèyàn bá mú ẹbọ tí wọ́n fẹ́ sun lórí pẹpẹ wá, àwọn àlùfáà burúkú náà á ní káwọn ìránṣẹ́ àwọn fúngun mọ́ àwọn tó mú ohun ìrúbọ wá, pé kí wọ́n fún àwọn ní ẹran tútù, kí wọ́n tiẹ̀ tó fi ọ̀rá rúbọ sí Jèhófà pàápàá.—Léfítíkù 3:3-5; 1 Sámúẹ́lì 2:13-17.