Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Gẹ́gẹ́ bí àwọn ọ̀mọ̀wé kan ṣe sọ, àkànlò èdè Hébérù tá a túmọ̀ sí “jọ̀wọ́ mi” nínú Ẹ́kísódù 32:10 la lè wò ó gẹ́gẹ́ bí ìkésíni, ìyẹn ni pé kí Ọlọ́run gba Mósè láyè láti bá wọn bẹ̀bẹ̀, tàbí ‘kí ó dúró sí àlàfo,’ tó wà láàárín Jèhófà àti orílẹ̀-èdè náà. (Sm. 106:23; Ìsík. 22:30) Ohun yòówù kí ọ̀rọ̀ náà jẹ́, ará rọ Mósè láti sọ èrò rẹ̀ jáde fàlàlà fún Jèhófà.