Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a A sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn kan lára ohun tó ń ṣẹlẹ̀ nínú ìjọ Kristẹni ní ọ̀rúndún kìíní máa dópin. Bí àpẹẹrẹ, a kò “sọ̀rọ̀ ní àwọn ahọ́n àjèjì” mọ́, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì “sọ tẹ́lẹ̀” mọ́. (1 Kọ́r. 13:8; 14:5) Síbẹ̀ náà, ìtọ́ni Pọ́ọ̀lù fún wa ní ìjìnlẹ̀ òye nípa bó ṣe yẹ ká máa darí àwọn ìpàdé ìjọ lónìí.