Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Tẹ́lẹ̀tẹ́lẹ̀, orúkọ tí Ábúráhámù ń jẹ́ ni Ábúrámù, Sárà sì ń jẹ́ Sáráì. Nígbà tó yá, Ọlọ́run yí orúkọ Ábúrámù pa dà sí Ábúráhámù, tó túmọ̀ sí “baba ogunlọ́gọ̀,” ó sì yí orúkọ Sáráì pa dà sí Sárà, tó túmọ̀ sí “Ìyá Ọba.” (Jẹ́nẹ́sísì 17:5, 15) Àmọ́ torí kó lè rọrùn, a máa pè wọ́n ní Ábúráhámù àti Sárà nínú àwọn àpilẹ̀kọ tó wà nínú ìwé yìí.