Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ọba yọ̀ǹda pé kí àwọn Júù tún lo ọjọ́ kejì láti fi pa àwọn ọ̀tá wọn yòókù run. (Ẹ́sítérì 9:12-14) Títí dòní, àwọn Júù ṣì ń ṣe ìrántí ìṣẹ́gun yẹn ní ìgbà ìrúwé. Wọ́n ń pe ayẹyẹ yẹn ní Púrímù, ìyẹn orúkọ kèké tí Hámánì ṣẹ́ nígbà tó pète láti run gbogbo ọmọ Ísírẹ́lì.