Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn orílẹ̀-èdè méjì tó para pọ̀ di agbára ayé náà ti wà láti ọ̀rúndún kejìdínlógún [18], àmọ́ ìran tí Jòhánù rí fi hàn pé àwọn méjèèjì máa di agbára ayé kan ṣoṣo ní ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ Olúwa. Ní tòótọ́, “ọjọ́ Olúwa” ni àsọtẹ́lẹ̀ tó wà lákọsílẹ̀ nínú ìwé Ìṣípayá ní ìmúṣẹ. (Ìṣí. 1:10) Ìgbà Ogun Àgbáyé Kìíní ni ìkeje lára orí ẹranko ẹhànnà náà bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ pa pọ̀ gẹ́gẹ́ bí agbára ayé kan ṣoṣo.