Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Ó wúni lórí láti rí i pé Rúùtù kò kàn lo orúkọ òye náà “Ọlọ́run” nìkan bí ọ̀pọ̀ àwọn ará ilẹ̀ òkèèrè ṣe sábà máa ń ṣe. Ó tún lo orúkọ Ọlọ́run gan-an, ìyẹn Jèhófà. Ìwé náà,The Interpreter’s Bible sọ pé: “Òǹkọ̀wé Bíbélì yẹn wá jẹ́ kó ṣe kedere pé Ọlọ́run tòótọ́ ni ará ilẹ̀ òkèèrè yìí ń sìn.”