Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
e Ìpínrọ̀ 14: Òye tuntun lèyí jẹ́ nípa Mátíù 13:42. Tẹ́lẹ̀, a sọ nínú àwọn ìwé wa pé àwọn Kristẹni afàwọ̀rajà yìí ti ń sunkún tí wọ́n sì ń payín keke fún ọ̀pọ̀ ọdún torí bí “àwọn ọmọ Ìjọba náà” ṣe ń jẹ́ káwọn èèyàn mọ̀ pé “àwọn ọmọ ẹni burúkú náà” ni wọ́n jẹ́. (Mát. 13:38) Àmọ́ o, ẹ kíyè sí i pé ìgbà tí Ọlọ́run bá máa pa wọ́n run ni wọ́n tó máa payín keke.—Sm. 112:10.