Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àwọn olùwádìí kan sọ pé ohun tó wà lọ́kàn àwọn ẹ̀gbọ́n Jósẹ́fù ni pé bí Jékọ́bù bàbá àwọn ṣe dá Jósẹ́fù lọ́lá yẹn fi hàn pé ó fẹ́ gbé ipò àkọ́bí fún Jósẹ́fù. Wọ́n mọ̀ pé Jósẹ́fù ni àkọ́bí ìyàwó tí Jékọ́bù fẹ́ràn jù, ìyá Jósẹ́fù sì ni bàbá wọn ì bá kọ́kọ́ fẹ́. Bákan náà, Rúbẹ́nì tó jẹ́ àkọ́bí Jékọ́bù ti ba ara ẹ̀ lórúkọ jẹ́, ó sì pàdánù ogun rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí i àkọ́bí nígbà tó bá ọ̀kan nínú àwọn ìyàwó bàbá rẹ̀ sùn tó sì tipa bẹ́ẹ̀ dójú ti bàbá rẹ̀.—Jẹ́nẹ́sísì 35:22; 49:3, 4.