Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
g Nígbà tí Jésù ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ọjọ́ ìkẹyìn, ó sọ pé: “Àwọn orílẹ̀-èdè yóò tẹ Jerúsálẹ́mù [èyí tó dúró fún ìṣàkóso Ọlọ́run] mọ́lẹ̀, títí àwọn àkókò tí a yàn kalẹ̀ fún àwọn orílẹ̀-èdè yóò fi pé.” (Lúùkù 21:24) Nípa bẹ́ẹ̀, ìṣàkóso Ọlọ́run ò tíì gbérí pa dà ní àkókò tí Jésù wà láyé, ipò yìí sì máa bá a lọ títí di àwọn ọjọ́ ìkẹyìn.