Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Àpẹẹrẹ kan ni ìgbà tí àwọn ọmọ Ámálékì àtàwọn ọmọ Kénáánì ṣẹ́gun àwọn ọmọ Ísírẹ́lì torí pé wọ́n kọ etí ikún sí ìkìlọ̀ tí Ọlọ́run fún wọn pé wọn ò gbọ́dọ̀ lọ ja ogun náà. (Númérì 14:41-45) Ọ̀pọ̀ ọdún lẹ́yìn èyí, Jòsáyà Ọba kù gìrì lọ sójú ogun tí Ọlọ́run kò fọwọ́ sí, ó sì bá ogun náà lọ.— 2 Kíróníkà 35:20-24.