Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ẹ̀rí fi hàn pé èyí tó pọ̀ jù lára àwọn tó wà níbẹ̀ di Kristẹni. Nígbà tí Pọ́ọ̀lù ń sọ̀rọ̀ nípa wọn nínú lẹ́tà rẹ̀ sí àwọn ará ní Kọ́ríńtì ó pè wọ́n ní “ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta àwọn ará.” Ó wá fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: ‘Púpọ̀ jù lọ nínú wọn ṣì wà títí di ìsinsìnyí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn nínú ikú.’ Torí náà, ó jọ pé Pọ́ọ̀lù àtàwọn Kristẹni míì ní ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní mọ ọ̀pọ̀ lára àwọn tí Jésù pàṣẹ náà fún ní tààràtà.