Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ìwé kan sọ pé ijó fìdígbòdí ni kí “obìnrin kan tó wọ aṣọ péńpé jókòó sórí ẹsẹ̀ ọkùnrin kan tó jẹ́ oníbàárà, kó sì máa jó sọ́tùn-ún sósì lórí ẹsẹ̀ onítọ̀hún.” Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ipò àwọn nǹkan yàtọ̀ síra, tírú nǹkan bẹ́ẹ̀ bá ṣẹlẹ̀, àwọn alàgbà máa gbé ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò dáadáa, kí wọ́n lè mọ̀ bóyá ọ̀rọ̀ náà burú débi tó fi máa gba pé kí wọ́n yan ìgbìmọ̀ onídàájọ́ láti bójú tó ọ̀rọ̀ náà. Tí Kristẹni kan bá ti lọ́wọ́ sí irú nǹkan bẹ́ẹ̀, ó yẹ kó lọ rí àwọn alàgbà kí wọ́n lè ràn án lọ́wọ́.—Ják. 5:14, 15.