Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ọ̀jọ̀gbọ́n C. Marvin Pate sọ pé: “Àwọn ọ̀mọ̀wé Bíbélì kan gbà pé nígbà tí Jésù lo ọ̀rọ̀ náà, ‘lónìí,’ ohun tó ń sọ ni pé láàárín wákàtí mẹ́rìnlélógún (24) ọjọ́ yẹn, òun máa kú, òun á sì lọ sí Párádísè.” Ọ̀jọ̀gbọ́n yìí wá fi kún un pé, “Ìṣòro ibẹ̀ ni pé àlàyé yìí ta ko àwọn ẹsẹ Bíbélì míì. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì sọ pé Jésù wà nínú Isà Òkú lẹ́yìn tó kú àti pé ẹ̀yìn-ọ̀-rẹyìn ló wá lọ sọ́run.”—Mát. 12:40; Ìṣe 2:31; Róòmù 10:7.