Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ó dáa ká máa rántí àwọn nǹkan tó ti ṣẹlẹ̀ sí wa rí nígbèésí ayé. Àmọ́ tó bá jẹ́ pé ìyẹn nìkan là ń rò ṣáá, ó lè mú ká dẹwọ́ nínú ohun tá à ń ṣe nínú ìjọsìn Jèhófà báyìí, ó sì lè má jẹ́ ká pọkàn pọ̀ sí ìrètí ọjọ́ iwájú mọ́. Téèyàn bá ń ronú ṣáá nípa àwọn nǹkan tó ti ṣẹlẹ̀ nígbèésí ayé ẹ̀, ṣe ló dà bí ìgbà tó ń wakọ̀ sẹ́yìn. Nínú àpilẹ̀kọ yìí, a máa jíròrò àwọn nǹkan mẹ́ta tó lè mú kéèyàn máa ṣe bẹ́ẹ̀. Àá sì jíròrò àwọn ìlànà Bíbélì àtàwọn àpẹẹrẹ òde òní tí kò ní jẹ́ ká máa ṣe bẹ́ẹ̀.