Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b Nígbà míì, ó máa ń pọn dandan fáwọn alàgbà láti gbọ́ ẹjọ́ àwọn tó dá ẹ̀ṣẹ̀ ńlá àtàwọn tó ronú pìwà dà. (1 Kọ́r. 5:11; 6:5; Jém. 5:14, 15) Síbẹ̀, ìrẹ̀lẹ̀ gbọ́dọ̀ mú kí wọ́n gbà pé àwọn ò lè mọ ohun tó wà lọ́kàn àwọn èèyàn, kí wọ́n sì máa rántí pé Jèhófà ni wọ́n ń ṣojú fún tí wọ́n bá ń dájọ́. (Fi wé 2 Kíróníkà 19:6.) Torí náà bíi ti Jèhófà, tí wọ́n bá ń dájọ́, wọ́n gbọ́dọ̀ fàánú hàn, wọn ò sì gbọ́dọ̀ ṣe ojúṣàájú.