Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Ẹsẹ Ìwé Mímọ́ tá a yàn fún ọdún 2023 máa fún ìgbàgbọ́ wa lókun gan-an, ó sọ pé: “Òtítọ́ ni kókó inú ọ̀rọ̀ rẹ.” (Sm. 119:160) Ó dájú pé ìwọ náà gbà bẹ́ẹ̀. Àmọ́ ọ̀pọ̀ ni ò gbà pé òtítọ́ lohun tó wà nínú Bíbélì àti pé ó lè tọ́ wa sọ́nà. Torí náà nínú àpilẹ̀kọ yìí, a máa jíròrò nǹkan mẹ́ta táá jẹ́ kí àwọn olóòótọ́ èèyàn gbà pé wọ́n lè gbára lé Bíbélì àti pé ó lè tọ́ wa sọ́nà.