Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
b ÀLÀYÉ Ọ̀RỌ̀: Àfojúsùn ni àwọn ìwà àtàwọn nǹkan míì tó o fẹ́ kó sunwọ̀n sí i tàbí àwọn nǹkan tó o fẹ́ ṣe nínú ìjọsìn Jèhófà, tó o sì ṣiṣẹ́ kára kọ́wọ́ ẹ lè tẹ̀ ẹ́. Ìyẹn lá jẹ́ kó o ṣe púpọ̀ sí i, kó o sì múnú Jèhófà dùn. Bí àpẹẹrẹ, ó lè wù ẹ́ pé kó o ní ànímọ́ Kristẹni kan tàbí kó o sunwọ̀n sí i nínú ọ̀kan lára àwọn apá ìjọsìn wa bíi kó o máa ka Bíbélì, kó o máa dá kẹ́kọ̀ọ́, kó o sì máa lọ sóde ìwàásù déédéé.