Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Nǹkan mẹ́ta ló ṣeé ṣe kí Dáníẹ́lì wò tí ò fi jẹ oúnjẹ àwọn ará Bábílónì. Àkọ́kọ́, ó ṣeé ṣe kí ẹran tí wọ́n fẹ́ kó jẹ wà lára àwọn ẹran tí Òfin Mósè sọ pé wọn ò gbọ́dọ̀ jẹ. (Diu. 14:7, 8) Ìkejì, ó ṣeé ṣe kí wọ́n má ro ẹ̀jẹ̀ ẹran náà dà nù dáadáa nígbà tí wọ́n pa á. (Léf. 17:10-12) Àti ìkẹta, ó ṣeé ṣe kó rò pé tóun bá jẹ oúnjẹ náà, wọ́n lè máa rò pé òun ti ń bá wọn jọ́sìn ọlọ́run èké wọn.—Fi wé Léfítíkù 7:15 àti 1 Kọ́ríńtì 10:18, 21, 22.