Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Nígbà míì, àwọn áńgẹ́lì máa ń ṣojú Jèhófà tí wọ́n bá ń jíṣẹ́ ẹ̀ fáwọn èèyàn. Ìdí nìyẹn tó fi jẹ́ pé nígbà míì, táwọn áńgẹ́lì bá ń sọ̀rọ̀, Bíbélì máa ń sọ ọ́ bíi pé Jèhófà fúnra ẹ̀ ló ń sọ̀rọ̀. (Jẹ́n. 18:1-33) Òótọ́ ni pé Ìwé Mímọ́ sọ pé Jèhófà ló fún Mósè ní Òfin, àmọ́ àwọn ẹsẹ Bíbélì míì jẹ́ ká mọ̀ pé àwọn áńgẹ́lì ni Jèhófà lò láti fún Mósè ní Òfin náà.—Léf. 27:34; Ìṣe 7:38, 53; Gál. 3:19; Héb. 2:2-4.