Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
a Olóòótọ́ ni Jóòbù, àmọ́ nígbà táwọn ọ̀rẹ́ ẹ̀ mẹ́ta sọ pé ó ti ṣe nǹkan tí ò dáa, ó bẹ̀rẹ̀ sí í ronú nípa ojú táwọn èèyàn fi ń wo òun. Nígbà táwọn ọmọ ẹ̀ kú, tó sì pàdánù gbogbo ohun ìní ẹ̀, “Jóòbù ò dẹ́ṣẹ̀, kò sì fẹ̀sùn kan Ọlọ́run pé ó ṣe ohun tí kò dáa.” (Jóòbù 1:22; 2:10) Àmọ́ nígbà tí wọ́n fẹ̀sùn kàn án, ó sọ “ọ̀rọ̀ ẹhànnà.” Bó ṣe máa gbèjà ara ẹ̀, tórúkọ ẹ̀ ò sì ní bà jẹ́ ló ṣe pàtàkì lójú ẹ̀ ju bó ṣe máa sọ orúkọ Ọlọ́run di mímọ́.—Jóòbù 6:3; 13:4, 5; 32:2; 34:5.