Àlàyé Ìsàlẹ̀ Ìwé
c Bó ṣe wà nínú Bíbélì NIV tó wà fún ìkẹ́kọ̀ọ́, bí wọ́n ṣe lo orúkọ Ọlọ́run léraléra nínú àwọn ẹsẹ yìí “jẹ́ ká rí bí orúkọ náà ti ṣe pàtàkì tó bó ṣe wà ní [ẹsẹ 27].” Àmọ́, àwọn kan sọ pé bí orúkọ Ọlọ́run ṣe fara hàn nígbà mẹ́tà nínú àwọn ẹsẹ yìí fi hàn pé Ọlọ́run jẹ́ Mẹ́talọ́kan. Àmọ́, kì í ṣe bọ́rọ̀ ṣe rí nìyẹn. Ìwé kan tó ń ṣàlàyé Bíbélì sọ pé “àwọn àlùfáà tó ń súre àtàwọn èèyàn tí wọ́n ń súre fún ò ní jẹ́ gbà láé pé bí wọ́n ṣe lo orúkọ Ọlọ́run lẹ́ẹ̀mẹ́ta túmọ̀ sí pé Ọlọ́run jẹ́ Mẹ́talọ́kan. Kàkà bẹ́ẹ̀, bí wọ́n ṣe tẹnu mọ́ orúkọ Ọlọ́run yìí túmọ̀ sí pé ìbùkún náà máa rí bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́.” (The Pulpit Commentary, ìdìpọ̀ kejì ojú ìwé 52) Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i, ka àpilẹ̀kọ náà “Ṣé Mẹ́talọ́kan ni Ọlọ́run?”