-
Ewu Tí Gbogbo Òbí Ń Kọminú Lé LóríJí!—2007 | October
-
-
Ewu Tí Gbogbo Òbí Ń Kọminú Lé Lórí
ỌLỌ́YÀYÀ èèyàn tí inú wọn sì máa ń dùn ni Fẹ́mi àti ìyàwó rẹ̀, Dúpẹ́. Ọmọ wọn ọkùnrin ti pé ọmọ ọdún mẹ́ta, ọmọ náà já fáfá, ara rẹ̀ sì le dáadáa.a Wọn ò fi ìtọ́jú jẹ ẹ́ níyà rárá. Ìyẹn kì í ṣe ohun tó rọrùn nínú ayé tá à ń gbé yìí ṣáá o. Béèyàn ṣe ń já sókè lá á máa já sódò, ojúṣe ibẹ̀ ò sì kéré. Ọ̀pọ̀ nǹkan ni òbí gbọ́dọ̀ fi kọ́ ọmọ! Èyí tó gba Fẹ́mi àti Dúpẹ́ lọ́kàn jù lọ lára ojúṣe wọn gẹ́gẹ́ bí òbí rèé: Wọ́n fẹ́ láti dáàbò bo ọmọ wọn lọ́wọ́ àwọn tó ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe. Báwo ló ṣe jẹ́ bẹ́ẹ̀?
Dúpẹ́ tó jẹ́ ìyá ọmọ náà sọ pé: “Ọ̀dájú ni bàbá mi, ọ̀mùtípara ni, ó sì máa ń tètè fara ya. Ó máa ń lù mí játijàti, ó sì máa ń bá èmi àtàwọn àbúrò mi ṣèṣekúṣe.”b Àwọn ọ̀mọ̀ràn níbi gbogbo gbà pé irú ìṣekúṣe bẹ́ẹ̀ lè múni banú jẹ́ lọ́nà kíkorò. Abájọ tí Dúpẹ́ fi pinnu pé òun á dáàbò bo ọmọ òun! Ọkọ ẹ̀ náà sì ṣe tán láti bá a fọwọ́ sowọ́ pọ̀.
Bíbá tí wọ́n ń bá àwọn ọmọdé ṣèṣekúṣe ti wá di ohun tí ọ̀pọ̀ òbí ń ṣàníyàn lé lórí báyìí. Bóyá ìwọ náà sì wà lára wọn. Wọ́n lè má tíì bá ẹ ṣèṣekúṣe rí bíi ti Dúpẹ́, ìyàwó Fẹ́mi, kó o má sì mọ bó ṣe máa ń rí lára. Àmọ́, ó ṣeé ṣe kó o ti gbọ́ ìròyìn tó ń jáni láyà nípa bí ìwà tó ń kóni nírìíra náà ṣe gbilẹ̀ tó. Kárí ayé lọkàn àwọn òbí tí ò fọ̀rọ̀ ọmọ wọn ṣeré kì í ti í balẹ̀ bí wọ́n ṣe ń gbọ́ nípa nǹkan tó ń ṣẹlẹ̀ sáwọn ọmọdé níbi tí wọ́n ń gbé.
Abájọ, ẹnì kan tí iṣẹ́ ìwádìí rẹ̀ máa ń dá lórí fífi ìbálòpọ̀ fìtínà ẹni sọ nípa ibi tí bíbọ́mọdé ṣèṣekúṣe gogò dé, ó ní “ó jẹ́ ọ̀kan lára ohun tí ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì báni jù lọ tó tíì ṣẹlẹ̀ rí lákòókò tá à ń gbé yìí.” Ìròyìn tí ń bani nínú jẹ́ gbáà mà nìyẹn o! Àmọ́, ṣó yẹ kírú àwọn nǹkan bí èyí máa yani lẹ́nu? Kò jẹ́ jẹ́ ohun ìyàlẹ́nu fáwọn tó ń kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣàlàyé pé à ń gbé ní àkókò ìdààmú tí Bíbélì pè ní “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn,” tó kún fún ìwà “òǹrorò,” nínú èyí táwọn èèyàn á ti jẹ́ “olùfẹ́ ara wọn” tí wọ́n á sì jẹ́ “aláìní ìfẹ́ni àdánidá.”—2 Tímótì 3:1-5.
Ìṣòro tó ń muni lómi gbáà lọ̀rọ̀ ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe. Ìwà tó burú jáì ni fáwọn èèyàn kan láti máa wá àwọn ọmọdé tí wọ́n á bá ṣèṣekúṣe kiri. Báwọn òbí kan bá sì ṣe ń ronú nípa èyí, ńṣe lọkàn wọn máa ń dà rú. Ṣé a wá lè sọ pé ìṣòro yìí ti kọjá èyí ti apá àwọn òbí lè ká? Àbí àwọn ohun tó bọ́gbọ́n mu kan wà táwọn òbí lè ṣe kí wọ́n bàa lè dáàbò bo àwọn ọmọ wọn? Àwọn àpilẹ̀kọ tó kàn á tú iṣu ìdáhùn sáwọn ìbéèrè yìí désàlẹ̀ ìkòkò.
[Àwọn Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a A ti yí àwọn orúkọ tó wà nínú ọ̀wọ́ àpilẹ̀kọ yìí padà.
b Kí ọkùnrin tàbí obìnrin àgbàlagbà máa lo ọmọdé láti fi tẹ́ ìfẹ́ ara rẹ̀ fún ìbálòpọ̀ lọ́rùn ló ń jẹ́ bíbá ọmọdé ṣèṣekúṣe. Lára àṣà yìí náà ni ohun tí Bíbélì pè ní àgbèrè, tàbí por·neiʹa wà. Lára àwọn nǹkan tó túmọ̀ sí por·neiʹa ni fífọwọ́ pa ẹ̀yà ìbálòpọ̀, bíbáni lò pọ̀, fífi ẹnu pọ́n ẹ̀yà ìbálòpọ̀ lá, tàbí kí ọkùnrin máa ki nǹkan ọmọkùnrin rẹ̀ bọnú ihò ìdí obìnrin tàbí ọkùnrin bíi tiẹ̀. Àwọn nǹkan míì tó jẹ mọ́ ìṣekúṣe, bíi fífọwọ́ pani lọ́yàn, fífi ìṣekúṣe lọni, fífi àwòrán oníhòòhò han ọmọdé, yíyọjú wo ẹni tó bọ́ra sílẹ̀ tàbí yíyọjú wo àwọn tó ń bára wọn lò pọ̀ àti ṣíṣí ara sílẹ̀ níbi tí kò yẹ, lè já sí ohun tí Bíbélì dẹ́bi fún tó sì pè ní “ìwà àìníjàánu” tàbí fífi “ìwà ìwọra hu onírúurú ìwà àìmọ́ gbogbo.”—Gálátíà 5:19-21; Éfésù 4:19.
-
-
Bẹ́ Ẹ Ṣe Lè Dáàbò Bo Àwọn Ọmọ YínJí!—2007 | October
-
-
Bẹ́ Ẹ Ṣe Lè Dáàbò Bo Àwọn Ọmọ Yín
Ọ̀PỌ̀ lára wa ni kì í fẹ́ pẹ́ lórí ọ̀rọ̀ tó bá ti jẹ mọ́ bíbọ́mọdé ṣèṣekúṣe. Àwọn òbí kì í tiẹ̀ fẹ́ gbọ́ ohun tó jọ ọ́ nítorí pé ṣe ló máa ń bí wọn nínú! Àmọ́ bíbọ́mọdé ṣèṣekúṣe ti wá di ọ̀ràn sí gbogbo aráyé lọ́rùn báyìí o, ńṣe ni ràbọ̀ràbọ̀ rẹ̀ sì máa ń ba àwọn ọmọ láyé jẹ́. Bó bá rí bẹ́ẹ̀, ṣó wá yẹ ni ohun téèyàn ń gbé yẹ̀ wò? Ìwọ wò ó ná, kí lo rò pó ṣe pàtàkì lójú ẹ ju ààbò àwọn ọmọ ẹ lọ? O lè wá rí i nígbà náà pé ó kúkú sàn kó o mọ̀ nípa àwọn tó ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe nítorí pé ààbò ọmọ ẹ ló yẹ kójẹ ẹ́ lógún jù. Ohun tó o bá sì mọ̀ nípa ẹ̀ á ràn ẹ́ lọ́wọ́ gidigidi láti mú kí ewu fo àwọn ọmọ ẹ dá.
Bí bíbá ọmọdé ṣèṣekúṣe bá tiẹ̀ jẹ́ ohun ẹ̀gbin tó gbilẹ̀ jù bẹ́ẹ̀ lọ, má ṣe jẹ́ kó dún mọ̀huru mọ́ ẹ débi tó ò fi ní fẹ́ láti wá nǹkan ṣe sí i . Ó ṣe kò ṣe, o ṣì lágbára tó ju tọmọ ẹ lọ lórí ọ̀ràn náà, agbára tó jẹ́ pé lẹ́yìn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún lọmọ ẹ tó máa nírú ẹ̀. Látìgbà tó o ti dáyé, ọ̀pọ̀ ìmọ̀, ìrírí àti ọgbọ́n lo ti ní. Àwọn ohun tó o sì nílò láti ṣàṣeyọrí náà nìyẹn. Ẹnu pé kó o lò wọ́n láti dáàbò bo ọmọ ẹ ló kù. Ní báyìí, a óò jíròrò àwọn ohun mẹ́ta tí gbogbo òbí lè ṣe sí ọ̀ràn náà. Àwọn rèé: (1) Ìwọ ni kó o jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tọ́mọ ẹ á lè rí sá tọ̀, (2) jẹ́ káwọn ọmọ ẹ mọ gbogbo ohun tó yẹ kí wọ́n mọ̀ nípa ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe, àti (3) kọ́ àwọn ọmọ ẹ lóhun tí wọ́n lè fi gbara wọn sílẹ̀.
Ṣé Ìwọ Lẹni Àkọ́kọ́ Tọ́mọ Ẹ Lè Rí Sá Tọ̀?
Ojúṣe àwọn òbí ni láti dáàbò bo àwọn ọmọ lọ́wọ́ ìṣekúṣe, kì í ṣe ojúṣe àwọn ọmọ fúnra wọn. Nítorí náà, àwọn òbí gan-an ló yẹ kí wọ́n kọ́kọ́ mọ ohun tó yẹ ní ṣíṣe, lẹ́yìn náà lọ̀rọ̀ á tó wá kan àwọn ọmọ. Bó o bá jẹ́ òbí, àwọn ohun díẹ̀ wà tó yẹ kó o mọ̀ nípa ìbọ́mọdé ṣèṣekúṣe. Ó yẹ kó o mọ irú àwọn èèyàn tó máa ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe àti ọ̀nà tí wọ́n ń gbé e gbà. Èrò àwọn òbí nípa àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ni pé wọ́n sábà máa ń jẹ́ ẹni táwọn ọmọdé ò mọ̀ rí ṣùgbọ́n tí wọ́n á fòru bojú, tí wọ́n á sì yọ́ kẹ́lẹ́ wọlé láti wá jí àwọn ọmọdé gbé kí wọ́n lè lọ fipá bá wọn lò pọ̀. Àwọn erìkìnà tó bá àpèjúwe yìí mu wà ní tòótọ́. A sì sábà máa ń gbọ́ nípa wọn nínú ìròyìn. Àmọ́, irú wọn ò fi bẹ́ẹ̀ wọ́pọ̀. Nínú gbogbo abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe mẹ́wàá, mẹ́sàn-án ló sábà máa ń jẹ́ ẹni tọ́mọ náà mọ̀ dáadáa tó sì fọkàn tán.
Ká sòótọ́, kò sẹ́ni táá fẹ́ gbà gbọ́ pé aládùúgbò tó kóni mọ́ra, olùkọ́, òṣìṣẹ́ ìlera, olùdánilẹ́kọ̀ọ́, tàbí ìbátan òun lè máa rokàn ìbálòpọ̀ sọ́mọ òun. Ná, kì í ṣe gbogbo èèyàn ló rí bẹ́ẹ̀ yẹn. Nítorí náà, kì í ṣe pé kó o wá bẹ̀rẹ̀ sí í fura sí tẹbí, tará àtàwọn ọ̀rẹ́ tó yí ẹ ká o. Síbẹ̀ náà, o lè dáàbò bo ọmọ rẹ bí ìwọ fúnra rẹ bá mọ ọgbọ́n táwọn tó ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe ń dá.—Wo àpótí tó wà lójú ìwé 6.
Bí ìwọ tó o jẹ́ òbí bá mọ ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí tí wọ́n ń lò, wàá lè jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tọ́mọ ẹ á lè máa rí sá tọ̀. Bí àpẹẹrẹ, bí ẹnì kan tó fẹ́ràn láti máa wà pẹ̀lú àwọn ọmọdé ju àwọn àgbà lọ bá kúndùn àti máa wà pẹ̀lú ọmọ ẹ, tó ń ra ẹ̀bùn fún un, tàbí tó sọ pé òun á máa bá ẹ bójú tó o, tó sì máa ń dá mú un jáde, kí ni wàá ṣe? Ṣé kíá lo ti máa gbà pé abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe nirú ẹni bẹ́ẹ̀? Ó tì o. Má ṣe jẹ́ kó yá ẹ jù láti ronú pé bónítọ̀hún ṣe jẹ́ nìyẹn. Ó lè jẹ́ pé ó kàn ń ṣe tiẹ̀ lásán ni o. Síbẹ̀ náà, má ṣe gbàgbé pé tojú tìyẹ́ làparò fi ń ríran. Bíbélì ṣáà sọ pé: “Ẹnikẹ́ni tí ó jẹ́ aláìní ìrírí ń ní ìgbàgbọ́ nínú gbogbo ọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n afọgbọ́nhùwà máa ń ronú nípa àwọn ìṣísẹ̀ ara rẹ̀.”—Òwe 14:15.
Rántí pé, ìwọ̀nba díẹ̀ lohun tó dáa dùn mọ o. Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ láti máa dá wà pẹ̀lú ọmọ ẹ ṣáá, rí i pó o mọ onítọ̀hún dáadáa. Jẹ́ kírú ẹni bẹ́ẹ̀ mọ̀ pé ìgbàkigbà lo lè wá bẹ ọmọ ẹ wò. Òbí tó ṣì ń tọ́ ọmọkùnrin mẹ́ta lọ́wọ́ ni Títí àti Dàmọ́lá, àmọ́ ọwọ́ kékeré kọ́ ni wọ́n fi mú ọ̀ràn jíjẹ́ kí ọmọ wọn máa dá wà pẹ̀lú àgbàlagbà. Nígbà tí ẹnì kan wá ń kọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọ wọn ọkùnrin lórin nílé, Melissa sọ fún olùkọ́ náà pé: “Mi ò ní yé máa wá wò yín títí tí wàá fi ṣe tán.” Ó lè dà bíi pé àṣejù ti wọ ọ̀ràn náà, àmọ́ ṣe kò dáa báwọn òbí yìí ṣe fi àbámọ̀ ṣáájú ọ̀ràn.
Má ṣe dá ọmọ ẹ dá gbogbo ohun tó bá ń ṣe, mọ àwọn tó ń bá ṣọ̀rẹ́, máa bá a dá sí iṣẹ́ tí wọ́n bá gbé fún un nílé ìwé. Mọ gbogbo bí wọ́n ṣe fẹ́ rìn bó bá ṣẹlẹ̀ pé ilé ẹ̀kọ́ fẹ́ kó wọn rìnrìn àjò lọ síbì kan. Ògbógi kan tó jẹ́ oníṣègùn ọpọlọ tó sì ti fi ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n tọ́jú onírúurú èèyàn tí wọ́n bá ṣèṣekúṣe sọ pé àìmọye irú ìṣekúṣe bẹ́ẹ̀ ni kì bá tí wáyé ká sọ pé àwọn òbí wà lójú fò. Ó ní abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe kan tí wọ́n ti dájọ́ fún sọ pé: “Àwọn òbí gan-an ni wọ́n ń fọwọ́ ara wọn fa àwọn ọmọ wọn lé wa lọ́wọ́. . . . Àwọn gan-an ni wọ́n mú kó rọrùn fún mi.” Má ṣe gbà gbé pé àwọn ọmọ tó bá rọrùn láti bá ṣèṣekúṣe lọ̀pọ̀ lára wọn máa ń wá kiri. Kì í rọrùn fún wọn láti dójú sọ àwọn ọmọ táwọn òbí wọn kì í sábà fi sílẹ̀ láwọn nìkan.
Ọ̀nà míì tó o lè gbà mú kó rọrùn fọ́mọ ẹ láti rí ẹ bí ẹni tó lè máa sá tọ̀ ni pé kó o máa tẹ́tí sí i dáadáa. Àwọn ọmọdé kì í sábà sọ bí ẹnikẹ́ni bá bá wọn ṣèṣekúṣe; ojú máa ń tì wọ́n jù, ẹ̀rù ohun táwọn ẹlòmíì á sọ sì máa ń bà wọ́n. Nítorí náà, fetí sílẹ̀ dáadáa, ì báà tiẹ̀ jẹ́ àmì kékeré kan lo rí.a Bí ọmọ ẹ bá sọ ohun kan tí kò fi ẹ́ lọ́kàn balẹ̀, fara balẹ̀ fi ìbéèrè wá a lẹ́nu wò.b Bó bá sọ pé òun ò fẹ́ kẹ́ni tẹ́ ẹ ni kó máa wá dúró ti òun nílé wá mọ́, bi í pé kí nìdí tó fi sọ bẹ́ẹ̀. Bó bá sọ pé eré tí àgbàlagbà kan ń bá òun ṣe ò ye òun tó, bi í pé: “Irú eré wo leré náà? Kí lonítọ̀hún ṣe gan-an?” Bó bá sọ pé ẹnì kan fọwọ́ kan òun, bi í pé, “Ibo ló fọwọ́ kàn lára ẹ?” Má máa tètè fojú kò-tó-nǹkan wo ìdáhùn tọ́mọ ẹ bá fún ẹ. Àwọn tó ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe sábà máa ń sọ fáwọn ọmọ náà pé kò sẹ́ni tó máa gba ohun tí wọ́n bá sọ gbọ́; lọ́pọ̀ ìgbà sì rèé, ohun tó máa ń ṣẹlẹ̀ gan-an nìyẹn. Bó bá sì ṣẹlẹ̀ pé wọ́n bá ọmọdé kan ṣèṣekúṣe, báwọn òbí ò bá ṣáà ti ka ọmọ náà sí onírọ́ tí wọn ò sì jáwọ́ lọ́rọ̀ ẹ̀, ó máa tètè bọ̀ sípò.
Kọ́ Ọmọ Ẹ Lóhun Tó Yẹ Kó Mọ̀ Nípa Ìbọ́mọdé-Ṣèṣekúṣe
A rí ohun tí abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe kan tí wọ́n ti dájọ́ fún sọ nínú ìwé kan tá a ti ṣèwádìí. Ó sọ pé: “Bí mo bá rí ọmọdé kan tí kò mọ ohunkóhun nípa ìbálòpọ̀, ọwọ́ mi ti ba ohun tí mò ń wá nìyẹn.” Ìránnilétí pàtàkì lọ̀rọ̀ tí ń bani lẹ́rù yìí jẹ́ fáwọn òbí. Ó máa ń rọrùn fáwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe láti tan àwọn ọmọ tí ò bá mọ ohunkóhun nípa ìbálòpọ̀ jẹ. Bíbélì sọ pé ìmọ̀ àti ọgbọ́n lè gbà wá “lọ́wọ́ ẹni tí ń sọ àwọn ohun àyídáyidà.” (Òwe 2:10-12) Àbí irú ààbò tó ò ń fẹ́ fọ́mọ ẹ kọ́ nìyẹn? Yàtọ̀ síyẹn, ọ̀nà pàtàkì kejì tó o lè gbà dáàbò bo ọmọ ẹ ni pé kó o má ṣe fà sẹ́yìn láti máa kọ́ ọ nípa kókó pàtàkì tá à ń sọ̀rọ̀ rẹ̀ yìí.
Ọ̀nà wo lo wá lè gbé e gbà? Ọ̀pọ̀ òbí lara wọn máa ń kó tìọ̀ láti báwọn ọmọ wọn jíròrò ọ̀ràn ìbálòpọ̀. Ó lè máa ti ọmọ ẹ pàápàá lójú láti jíròrò nípa ìbálòpọ̀, kó tiẹ̀ dà bíi pé kò fẹ́ láti bá ẹ sọ ohun tó jọ ọ́. Nítorí náà, ìwọ ni kó o kọ́kọ́ dá ọ̀rọ̀ náà sílẹ̀. Títí sọ pé: “A tètè bẹ̀rẹ̀ sí í kọ́ wọn lórúkọ táwọn ẹ̀yà ara kọ̀ọ̀kan ń jẹ́. À ń pè wọ́n lórúkọ tí wọ́n ń jẹ́ gan-an, a ò dà wọ́n pè rárá, kó bàa lè yé wọn pé kò sóhun tó ṣàjèjì tàbí ohun tó ń tini lójú nípa ẹ̀yà èyíkéyìí lára wọn.” Bíbẹ̀rẹ̀ lọ́nà yìí máa ń jẹ́ kó rọrùn láti fún wọn ní ìtọ́ni nípa àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe. Ọ̀pọ̀ òbí á wulẹ̀ sọ fáwọn ọmọ wọn pé ibi tí wọ́n máa ń fi aṣọ ìnura bò lára wọn yẹn ṣe pàtàkì gan-an ni, ẹlòmíì ò sì lẹ́tọ̀ọ́ láti fọwọ́ kan ibẹ̀.
Dúpẹ́ tá a sọ̀rọ̀ ẹ̀ níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ yìí sọ pé: “Èmi àti Baálé mi sọ fún ọmọ wa ọkùnrin pé okó ẹ̀ kì í ṣe bèbí ìṣeré, tiẹ̀ nìkan ni. Ẹnikẹ́ni ò gbọ́dọ̀ máa fọwọ́ gbé e ṣiré, ì báà jẹ́ àwa òbí ẹ tàbí dókítà pàápàá. Nígbà tá a gbé e lọ sọ́dọ̀ dókítà, mo ṣàlàyé fún un pé iṣẹ́ dókítà ni láti rí sí i pé ara rẹ yá, nítorí ìyẹn nìkan ló fi lè fọwọ́ kan ibẹ̀.” Àwọn òbí méjèèjì ni wọ́n máa ń dígbà bá ọmọ náà sọ̀rọ̀ yìí, wọ́n sì máa ń fi í lọ́kàn balẹ̀ pé gbogbo ìgbà tí ẹnikẹ́ni bá fọwọ́ kàn án níbi tí kò yẹ tàbí tí wọ́n bá ṣe ohun tó ni ín lára ni kó máa wá sọ fáwọn. Àwọn ògbógi nípa ìtọ́jú ọmọ àti béèyàn ṣe lè dènà ìbọ́mọdé ṣèṣekúṣe dábàá pé káwọn òbí máa báwọn ọmọ wọn sọ irú ọ̀rọ̀ yìí.
Ọ̀pọ̀ èèyàn ti rí i pé ìwé Kẹ́kọ̀ọ́ Lọ́dọ̀ Olùkọ́ Ńlá Náàc máa ran àwọn òbí lọ́wọ́ gan-an láti kọ́ àwọn ọmọ wọn nípa kókó yìí. Orí 32, “Bí Ọlọ́run Ṣe Dáàbò Bo Jésù,” ní àlàyé tààràtà tó lè fi àwọn ọmọdé lọ́kàn balẹ̀ lórí ọ̀ràn ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe àti bó ṣe ṣe pàtàkì tó fún wọn láti máa dáàbò bo ara wọn. Títí sọ pé: “Ìwé náà ti jẹ́ ká mọ ọ̀nà tó dáa gan-an tá a lè gbà fìdí ohun tá a ti sọ fáwọn ọmọ wa múlẹ̀.”
Nínú ayé tá à ń gbé lónìí, ó yẹ ká kọ́ àwọn ọmọdé pé àwọn èèyàn kan wà tí wọ́n á fẹ́ máa fọwọ́ kan wọ́n níbi tí kò yẹ tàbí tí wọ́n á fẹ́ káwọn ọmọdé máa fọwọ́ kan ibi tí kò yẹ lára tiwọn. Kò yẹ kí ìkìlọ̀ yìí mú káwọn ọmọdé máa bẹ̀rù tàbí kó mú kí wọ́n máa sá fáwọn àgbàlagbà. Heather sọ pé: “Ààbò àwọn ọmọ ni irú ìkìlọ̀ yìí wà fún. Ọ̀kan ṣoṣo ló sì jẹ́ lára ọ̀pọ̀ ìkìlọ̀ mìíràn tí ọ̀pọ̀ lára wọn ò ní í ṣe pẹ̀lú ìṣekúṣe. Kò ba ọmọ mi lẹ́rù rárá ni.”
Lára ohun tó yẹ kó o jẹ́ kọ́mọ ẹ mọ̀ ni pé kì í ṣe gbogbo ohun tẹ́nì kan bá ní kó ṣe náà ló gbọ́dọ̀ máa ṣe. Ẹ̀kọ́ pàtàkì tó sì nira ni láti kọ́ ọmọ pé kó jẹ́ onígbọràn. (Kólósè 3:20) Àmọ́ ṣá o, àṣejù lè wọ irú ẹ̀kọ́ bẹ́ẹ̀. Bá a bá kọ́ ọmọ kan pé lábẹ́ ipò èyíkéyìí, ó gbọ́dọ̀ máa ṣègbọràn sí àgbàlagbà èyíkéyìí ní gbogbo ìgbà, irú ọmọ bẹ́ẹ̀ ò ní pẹ́ bọ́ sọ́wọ́ àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe. Àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe tètè máa ń kíyè sí àwọn ọmọdé tí wọ́n bá máa ń yára ṣègbọràn jù. Àwọn òbí tó gbọ́n máa ń kọ́ àwọn ọmọ wọn pé kì í ṣe gbogbo èèyàn ló yẹ kí wọ́n máa ṣègbọràn sí, pàápàá bónítọ̀hún bá ní kí wọ́n ṣe ohun tí kò dáa. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìyẹn lè dún bí ohun tó ṣòroó ṣe, lójú àwa tá a jẹ́ Kristẹni ohun tó rọrùn gbáà ni. Ohun tó túmọ̀ sí ò ju pé kó o sọ fọ́mọ ẹ pé: “Bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún ẹ pé kó o ṣe ohun tí Jèhófà Ọlọ́run sọ pé ó burú, o ò gbọ́dọ̀ ṣe é o. Kódà, àwa tá a jẹ́ òbí ẹ gan-an ò gbọ́dọ̀ sọ pé kó o ṣe ohun tí Jèhófà sọ pé ó burú. Gbogbo ìgbà tẹ́nì kan bá sì ń fẹ́ kó o ṣe ohun tí kò dáa ni kó o máa jẹ́ káwa òbí ẹ gbọ́.”
Lákòótán, jẹ́ kọ́mọ ẹ mọ̀ pé kò sẹ́ni tó gbọ́dọ̀ sọ fún un pé kó pa ọ̀rọ̀ mọ́ láṣìírí fún ẹ. Sọ fún un pé bí ẹnikẹ́ni bá ní kó pa ohunkóhun mọ́ láṣìírí fún ẹ, ṣe ni kó máa wá sọ nǹkan náà fún ẹ. Ká tiẹ̀ wá sọ pé onítọ̀hún fi ohunkóhun dẹ́rù bà á tàbí kó jẹ́ pé òun fúnra rẹ̀ ti ṣe ohun kan tó kù díẹ̀ káàtó, jẹ́ kó mọ̀ pé kò sígbà kankan tó burú pé kó wá fi ẹjọ́ onítọ̀hún sun ẹ̀yin tẹ́ ẹ jẹ́ òbí rẹ̀. Kò yẹ kí irú ìtọ́ni bí èyí bà á lẹ́rù. O lè fi í lọ́kàn balẹ̀ pé ọ̀pọ̀ èèyàn ò ní jẹ́ fọwọ́ kàn án níbi tí kò yẹ, tàbí kí wọ́n sọ fún un pé kó ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run, tàbí kí wọ́n sọ fún un pé kó pa ohun kan mọ́ láṣìírí. Ńṣe ni àwọn ìkìlọ̀ tó dá lórí ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe yìí dà bí ìgbà téèyàn ń ronú nípa ibi tó máa gbà sá jáde bí iná bá ń jó. Ìmúrasílẹ̀ ni gbogbo ẹ̀ wà fún, ó ṣeé ṣe kí ohun tó máa mú kó fi ìkìlọ̀ náà sílò má tiẹ̀ wáyé rárá.
Kọ́ Ọmọ Ẹ Lóhun Tó Lè Fi Gbara Ẹ̀ Sílẹ̀
Ohun kẹta tá a máa jíròrò báyìí ni pé kó o jẹ́ kọ́mọ ẹ mọ àwọn nǹkan díẹ̀-dìẹ̀-díẹ̀ tó lè ṣe bó bá ṣẹlẹ̀ pé ẹnikẹ́ni gbìyànjú láti bá a ṣe ohun tí kò tọ́ nígbà tó ò sí níbẹ̀. Ńṣe làwọn kan máa ń jẹ́ kó dà bí ìgbà téèyàn ń ṣeré. Àwọn òbí á béèrè pé “Kí lo máa ṣe bí . . . ?” Ọmọ náà á sì dáhùn nípa sísọ ohun tó máa ṣe. O tún lè bi í pé, “Ká sọ pé a jọ lọ ra nǹkan lọ́jà, tó ò sì ṣàdédé rí mi mọ́ ńkọ́? Báwo lo ṣe máa wá mi kàn?” Ìdáhùn ọmọ náà lè máà rí gẹ́lẹ́ bó o ṣe rò, àmọ́ o lè fàwọn ìbéèrè míì tọ́ ọ sọ́nà, bíi, “Ṣó o rò pé nǹkan míì wà tí ì bá dára jù pé kó o ṣe?”
O lè lo àwọn ìbéèrè míì bẹ́ẹ̀ yẹn láti fi wádìí ohun tọ́mọ kan máa rò pé ó sàn jù kóun ṣe bí ẹnì kan bá gbìyànjú láti fọwọ́ kàn án níbi tí kò yẹ. Bírú ìbéèrè bẹ́ẹ̀ bá tètè máa ń já ọmọ ẹ láyà, o lè gbìyànjú láti sọ ìtàn kan fún un nípa ọmọ mìíràn. Bí àpẹẹrẹ: “Ọmọbìnrin kékeré kan wà pẹ̀lú ìbátan rẹ̀ kan tó fẹ́ràn, àmọ́ ẹni yẹn wá ń gbìyànjú láti fọwọ́ kàn án níbi ti kò yẹ. Kí lo rò pó dáa jù tí ì bá ṣe?”
Kí ló yẹ kó o kọ́ àwọn ọmọ ẹ pé kí wọ́n ṣe bọ́ràn bá rí bíi ti ọmọbìnrin kékeré tá a sọ̀rọ̀ ẹ̀ yìí? Òǹkọ̀wé kan sọ pé: “Bí wọ́n bá lọgun pé ‘Mi ò fẹ́ kéèyàn fọwọ́ kàn mí níbẹ̀ yẹn!’ tàbí ‘Ẹ má dán an wò!’ tàbí ‘Ẹ fi mi sílẹ̀!’ ẹ̀rù á tètè ba ẹni tó fẹ́ fọwọ́ síbi tí kò yẹ náà, á gbọ́wọ́ ẹ̀ padà, á sì wá ibòmíì gbà lọ.” Máa wá àyè díẹ̀díẹ̀ láti jẹ́ kọ́mọ ẹ fi bó ṣe máa ṣe hàn ẹ́. Èyí á jẹ́ kó lè nígboyà láti lọgun pé òun ò fẹ́rú ẹ̀, á lè tètè sá kúrò níbẹ̀, á sì lè tètè fẹjọ́ ohun tó ṣẹlẹ̀ sùn ẹ́. Bó bá tiẹ̀ dá bíi pé ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà ye ọmọ kan dáadáa, ó lè tètè gbàgbé ẹ̀ láàárín ọ̀sẹ̀ tàbí oṣù díẹ̀. Nítorí náà, máa tún ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà ṣe déédéé.
Gbogbo àwọn tó bá wà nípò láti máa tọ́jú ọmọ náà, tó fi mọ́ àwọn tó jẹ́ ọkùnrin lára wọn, ì báà jẹ́ bàbá ẹ̀, ọkọ ìyá ẹ̀, tàbí ìbátan míì tó jẹ́ ọkùnrin, ló yẹ kí ìjíròrò náà ṣojú wọn tàbí kí wọ́n mọ̀ nípa ẹ̀. Kí nìdí? Ìdí ni pé ohun tí gbogbo àwọn tó bá wà níbi ìdánilẹ́kọ̀ọ́ bẹ́ẹ̀ ń dọ́gbọ́n sọ ni pé àwọn ò ní jẹ́ bá irú ọmọ bẹ́ẹ̀ ṣèṣekúṣe. Ó bani nínú jẹ́ pé lábẹ́ ọ̀ọ̀dẹ̀ gan-an ni ọ̀pọ̀ ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ti máa ń wáyé. Àpilẹ̀kọ tó kàn lẹ́yìn èyí á sọ bó o ṣe lè mú kínú ilé jẹ́ ibi ààbò nínú ayé tí wọ́n ti ń bá àwọn ọmọdé ṣèṣekúṣe yìí.
[Àwọn Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a Àwọn ògbógi kíyè sí i pé bó tilẹ̀ jẹ́ pé ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ tí wọ́n bá ṣèṣekúṣe lè má sọ nǹkan kan, wọ́n ṣì máa ń fi hàn lọ́nà míì pé ẹnì kan ti báwọn ṣèṣekúṣe. Bí àpẹẹrẹ, bí ọmọ kan bá ṣàdédé bẹ̀rẹ̀ sí í hùwà tó ti fi sílẹ̀ nígbà tó wà lọ́mọdé, bíi kó máa tọ̀ sílé, kó máa lọ́ máwọn òbí ẹ̀ káàkiri, tàbí kí ẹ̀rù máa bà á láti dá wà, ìyẹn lè jẹ́ àpẹẹrẹ pé láburú kan tó ń bà á nínú jẹ́ ti ṣẹlẹ̀ sí i. Kò wá pọn dandan pé kéèyàn máa wo irú àpẹẹrẹ bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé wọ́n ti bá ọmọ náà ṣèṣekúṣe. Fara balẹ̀ wádìí lọ́dọ̀ ọmọ rẹ kó o bàa lè mọ ohun tó ń dà á lọ́kàn rú, kó o bàa lè sọ̀rọ̀ ìtùnú fún un, kó o mú un lọ́kàn lé, kó o sì dáàbò bò ó.
b Kí àlàyé tá à ń ṣe lè rọrùn, a ó máa sọ̀rọ̀ ẹni tó ń bọ́mọdé ṣèṣekúṣe àti ẹni tí wọ́n ń bá ṣèṣekúṣe bí ẹni pé ọkùnrin ni wọ́n. Àmọ́, tọkùnrin tobìnrin làwọn ìlànà tó wà nínú àpilẹ̀kọ yìí wúlò fún.
c Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la tẹ̀ ẹ́.
[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 5]
Jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tọ́mọ ẹ á lè rí sá tọ̀
[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 7]
Kọ́ ọmọ ẹ lóhun tó yẹ kó mọ̀ nípa ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe
[Ìsọfúnni tá a pàfiyèsí sí ní ojú ìwé 8]
Jẹ́ kọ́mọ ẹ mọ bó ṣe lè gbara ẹ̀ sílẹ̀
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 4]
ÌBỌ́MỌDÉ-ṢÈṢEKÚṢE TI DI ÌṢÒRO TÓ KÁRÍ AYÉ
Lọ́dún 2006, akọ̀wé àgbà fún Àjọ Ìparapọ̀ Orílẹ̀-Èdè jábọ̀ ohun tó ń ṣẹlẹ̀ lágbàáyé fún Àjọ Gbogbo Gbòò ti Ìparapọ̀ Orílẹ̀-Èdè. Ìròyìn tó jábọ̀ náà dá lórí àwọn ọmọdé táwọn èèyàn ń fipá mú ṣe ohun tí kò ti ọkàn wọn wá. Ògbógi kan tó ń dáṣẹ́ ṣe ló kó ìròyìn náà jọ fún Àjọ Ìparapọ̀ Orílẹ̀-Èdè. Gẹ́gẹ́ bí ìròyìn náà ṣe sọ, lọ́dún kan lẹ́nu àìpẹ́ yìí, àwọn ọmọbìnrin tó tó àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà àádọ́jọ [150,000,000] àtàwọn ọmọbìnrin tó tó àádọ́ta ọ̀kẹ́ lọ́nà mẹ́tàléláàádọ́rin [73,000,000] tí wọn ò tíì pé ọmọ ọdún méjìdínlógún ni wọ́n “fipá bá lò pọ̀ tàbí ni wọ́n fi agídí bá ní irú ìbálòpọ̀ èyíkéyìí mìíràn.” Iye yẹn mà ti pọ̀ jù o! Àmọ́, ìròyìn náà sọ síwájú sí i pé: “Ó ju iye yìí lọ dáadáa.” Àgbéyẹ̀wò tí wọ́n ṣe lórí ìwádìí kan tó ti orílẹ̀-èdè méjìlélógún wá fi hàn pé láwọn ibì kan, bá a bá kó ọgọ́rùn-ún obìnrin àti ọgọ́rùn-ún ọkùnrin jọ, mẹ́rìndínlógójì lára àwọn obìnrin náà àti mọ́kàndínlọ́gbọ̀n lára àwọn ọkùnrin náà ni wọ́n ti bá ṣèṣekúṣe rí, lọ́nà kan tàbí òmíràn, nígbà tí wọ́n wà lọ́mọdé. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ìbátan irú àwọn ọmọ bẹ́ẹ̀ ló pọ̀ jù lára àwọn tó bá wọn ṣèṣekúṣe!
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 6]
Ọ̀NÀ TÍ WỌ́N Ń GBÀ TAN ỌMỌDÉ JẸ
Abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ò ní ṣàìmọ̀ pé bóun bá fagbára ṣe é, ọwọ́ òun ò ní tẹ nǹkan tóun ń wá. Nítorí náà, á kúkú yàn láti máa tan ọmọ náà jẹ díẹ̀díẹ̀. Á kọ́kọ́ wá ọmọ tó máa dójú sọ, èyí tó sábà máa ń jẹ́ ọmọ tó dùn ún tàn jẹ, tó jẹ́ ẹni-o-rí-o-bá-lọ, táá sì ṣeé tì síbí tì sọ́hùn-ún. Lẹ́yìn náà, á wá bó ṣe máa dá wà lóhun nìkan pẹ̀lú ọmọ náà. Ó tún lè gbìyànjú láti fa ojú àwọn òbí ọmọ náà mọ́ra. Àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe mọ béèyàn ṣe ń díbọ́n gan-an ni. Wọ́n á máa ṣe bíi pé àwọn nífẹ̀ẹ́ ọmọ náà àtàwọn tó wà nínú ìdílé tọ́mọ náà ti wá.
Bọ́jọ́ ti ń gorí ọjọ́, abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe náà á bẹ̀rẹ̀ sí í gbára dì láti bá ọmọ náà ṣèṣekúṣe. Ní kẹ̀rẹ̀kẹ̀rẹ̀, á bẹ̀rẹ̀ sí i ṣe àwọn ohun tó lè mú kóun àtọmọ náà máa fara kanra, bíi kó jẹ́ kójú òun àti tọmọ náà máa ṣe mẹ́rin, kó máa fìfẹ́ hàn sí i, kó máa bá a ṣerépá, tàbí kó máa fọwọ́ kàn án lára. Ó lè máa ra ẹ̀bùn fún un kó sì bẹ̀rẹ̀ sí í fa ojú ọmọ náà mọ́ra débi pé á mú un kúrò láàárín àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, àwọn tẹ̀gbọ́n tàbúrò rẹ̀, àtàwọn òbí rẹ̀, kó bàa lè dá wà pẹ̀lú rẹ̀ lóun nìkan. Ó tiẹ̀ lè bá a débi tó fi máa sọ fún ọmọ náà pé kó máa pa àwọn àṣírí pẹ́ẹ́pẹ̀ẹ̀pẹ́ kan mọ́ fáwọn òbí ẹ̀. Á ní kò gbọ́dọ̀ sọ fún wọn pé òun ra nǹkan fún un, kò sì gbọ́dọ̀ jẹ́ kí wọ́n mọ̀ pé òun fẹ́ mú un jáde lọ síbì kan. Kò sí méjì lẹ́yìn irú ọgbọ́n ẹ̀wẹ́ bẹ́ẹ̀ ju pé kó lè bá ọmọ náà ṣèṣekúṣe lọ. Lẹ́yìn tí ọmọ náà àtàwọn òbí ẹ̀ bá ti wá gbára lé abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe náà tán pátápátá, kí àáyá rẹ̀ bẹ́ sílẹ̀, kó bẹ́ sáré ló kù.
Síbẹ̀ náà, ó ṣeé ṣe kó ṣì máa fọgbọ́n ṣe é dípò tí ì bá fi máa fi agbára tàbí agídí ṣe é. Ó lè lo àǹfààní ti pé ọmọ náà ò mọ púpọ̀ nípa ìbálòpọ̀ láti fi tàn án jẹ, kó wá máa ṣe bíi pé ṣe lòun ń kọ́ ọ, tàbí kó máa sọ fún un pé kó jẹ́ káwọn jọ ṣe eré àrà ọ̀tọ̀ kan tó jẹ́ pé àwọn méjèèjì nìkan làwọn máa mọ̀ nípa ẹ̀. Ó lè gbìyànjú láti fi àwòrán oníhòòhò han ọmọ náà kó bàa lè rò pé kò sóun tó burú nínú irú ìwà bẹ́ẹ̀.
Bó bá fi lè bá ọmọ náà ṣèṣekúṣe pẹ́nrẹ́n, ó di pé kó máa wá ọ̀nà tí ọmọ náà ò fi ní sọ fún ẹnikẹ́ni. Ó lè dá onírúurú ọgbọ́n, kó máa dẹ́rù ba ọmọ náà, kó máa sọ pé ohun á fẹjọ́ ẹ̀ sun àwọn òbí ẹ̀, kó máa dá a lẹ́bi, kódà gbogbo ohun tá a sọ yìí ló lè ṣe. Bí àpẹẹrẹ, ó lè sọ pé: “Ìwọ lo fà á. O ò sọ pé o ò fẹ́.” Ó tún lè sọ pé: “Bó o bá sọ fáwọn òbí ẹ, wọ́n á pe ọlọ́pàá, wọ́n á sì jù mí sẹ́wọ̀n títí láé.” Ó sì lè sọ pé: “Àárín èmi àti ẹ ni kó mọ o. Bó o bá sọ, kò sẹ́ni tó máa gbà ẹ́ gbọ́. Báwọn òbí ẹ bá fi lọ mọ̀ pẹ́nrẹ́n, màá ṣe wọ́n ní jàǹbá.” Kò sírú ọgbọ́nkọ́gbọ́n tàbí ọgbọ́n jàǹbá tírú ẹni bẹ́ẹ̀ ò lè dá.
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 5]
Má máa dá ọmọ ẹ dá ohun tó bá ń ṣe
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 7]
Rí i pé o kọ́ ọmọ ẹ lóhun tó yẹ kó mọ̀ nípa ìbálòpọ̀
[Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 8]
Kọ́ ọmọ ẹ pé kó má ṣe gba gbẹ̀rẹ́, kó sì kọ̀ jálẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ bá a ṣèṣekúṣe
-
-
Bẹ́ Ẹ Ṣe Lè Mú Kí Ilé Yín Jẹ́ Ibi ÀàbòJí!—2007 | October
-
-
Bẹ́ Ẹ Ṣe Lè Mú Kí Ilé Yín Jẹ́ Ibi Ààbò
Ọ̀RỌ̀ tó bani nínú jẹ́ gan-an ni Bíbélì lò láti fi ṣàlàyé bí ọ̀pọ̀ èèyàn á ṣe rí ní “àwọn ọjọ́ ìkẹyìn” tá à ń gbé yìí. Ó ní àwọn èèyàn á jẹ́ “aláìní ìfẹ́ni àdánidá.” (2 Tímótì 3:1, 3, 4) Ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe tó ń gbilẹ̀ nínú ìdílé báyìí jẹ́ ẹ̀rí tó ṣe kedere pé àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì yìí ń nímùúṣẹ. Ọ̀rọ̀ Gíríìkì tí Bíbélì lò ní ìpilẹ̀ṣẹ̀ yìí, ìyẹn aʹstor·gos, túmọ̀ sí “àìsí ìfẹ́ni àdánidá” lédè Gẹ̀ẹ́sì. Òdì kejì ló jẹ́ sí irú ìfẹ́ tó yẹ kó máa jọba láàárín àwọn tó ti inú ìdílé kan náà wá, pàápàá jù lọ ìfẹ́ tó yẹ kó wà láàárín àwọn òbí àtàwọn ọmọ.a Bẹ́ẹ̀ sì rèé, àárín àwọn tó bára wọn tan lọ́nà yìí gan-an ni ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ti máa ń wáyé.
Àwọn olùṣèwádìí kan sọ pé àwọn ọkùnrin ló sábà máa ń dá ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe láṣà nínú ilé. Irú ọkùnrin bẹ́ẹ̀ lè jẹ́ bàbá ọmọ náà, ọkọ míì tí ìyá ẹ̀ lọ fẹ́, tàbí ọkùnrin míì tó jẹ́ ìbátan tó sún mọ́ ọmọ náà. Ó tún wọ́pọ̀ pé káwọn ìbátan míì tó jẹ́ ọkùnrin máa bá àwọn ọmọdé ṣèṣekúṣe. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọmọdébìnrin ló pọ̀ jù lára àwọn tí wọ́n máa ń bá ṣèṣekúṣe, kò yọ àwọn ọmọdékùnrin náà sílẹ̀. Àwọn obìnrin tó jẹ́ abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe náà ò ṣaláì pọ̀ díẹ̀. Àfàìmọ̀ kó máa jẹ́ pé irú ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe táwọn èèyàn kì í sábà ròyìn ẹ̀ ni tàwọn tẹ̀gbọ́n tàbúrò tí wọ́n jọ ń gbé, síbẹ̀ tí wọ́n ń bára wọn sùn. Èyí àgbà tàbí èyí tó lágbára jù á fọgbọ́n tan èyí tó kéré sí i tàbí tí kò lágbára tó o lára àwọn àbúrò ẹ̀ ọkùnrin tàbí obìnrin, á sì bá a lò pọ̀. Ó dájú pé nǹkan ẹ̀gbin gbáà ni gbogbo ìyẹn á jẹ́ sí ẹ̀yin òbí.
Kí lẹ lè ṣe tírú àwọn ìṣòro bí èyí ò fi ní máa wáyé nínú ilé yín? Ohun kan tó dájú ni pé àwọn ìlànà kan wà tí ò fàyè gba bíbá ẹnikẹ́ni ṣèṣekúṣe. Ó dára kí gbogbo ẹni tó bá jẹ́ ara ìdílé èyíkéyìí kọ́ nípa àwọn ìlànà náà kí wọ́n sì mọrírì wọn. Inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí í ṣe Bíbélì nibi tó dára jù lọ tá a ti lè rí irú ìtọ́sọ́nà bẹ́ẹ̀.
Ohun Tí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Sọ Nípa Bó Ṣe Yẹ Ká Máa Bára Wa Gbé
Ọ̀nà tí gbogbo ìdílé lè gbà sá fún ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ni pé kí wọ́n máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà inú Bíbélì tó dá lórí bó ṣe yẹ ká máa hùwà. Bíbélì kì í fọ̀rọ̀ bọpo bọyọ̀ bó bá kan ọ̀rọ̀ nípa ìbálòpọ̀. Kì í sọ ọ́ ní àsọbàjẹ́, síbẹ̀ ó máa ń sọ ọ́ lọ́nà tó ṣe pàtó tó sì lọ sórí kókó. Ó fi hàn pé Ọlọ́run ṣètò ìbálòpọ̀ lọ́nà tó fi máa mú kí tọkọtaya gbádùn ara wọn. (Òwe 5:15-20) Àmọ́, kò fàyè gba kí àwọn tí kò gbéra wọn níyàwó máa bára wọn lò pọ̀. Bí àpẹẹrẹ, Bíbélì ò fàyè gba ìbálòpọ̀ láàárín ìbátan. Nínú Léfítíkù orí 18, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ onírúurú ìbálòpọ̀ láàárín ìbátan ni Ọlọ́run dẹ́bi fún. Kíyè sí àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ná: “Ọkùnrin èyíkéyìí nínú yín kò gbọ́dọ̀ sún mọ́ ẹnikẹ́ni tí ó jẹ́ ìbátan rẹ̀ tímọ́tímọ́ nípa ti ara láti tú u sí ìhòòhò [láti ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú rẹ̀]. Èmi ni Jèhófà.”—Léfítíkù 18:6.
Jèhófà ka ìbálòpọ̀ láàárín ìbátan mọ́ ara àwọn “ohun ìṣe-họ́ọ̀-sí” tó máa yọrí sí ikú fún ẹni tó bá dán an wò. (Léfítíkù 18:26, 29) Ó ṣe kedere pé ìlànà tí Ẹlẹ́dàá gbé kalẹ̀ lórí àwọn ọ̀ràn wọ̀nyí kì í ṣe èyí tá a lè fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn. Lónìí, ọwọ́ kan náà ni ọ̀pọ̀ àwọn alákòóso fi mú bíbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe nínú ìdílé, òfin wọn ò fàyè gbarú ẹ̀. Lọ́pọ̀ ìgbà, òfin máa ń sọ pé ohun tó bá fà á tí àgbàlagbà fi bá ọmọdé lò pọ̀, ó ti fipá bá a sùn nìyẹn. Kí nìdí tá a fi lè pe irú ẹ̀ ní ìfipá-báni-lòpọ̀ bí kò bá la ìfipá-múni lọ?
Ọ̀pọ̀ àwọn aláṣẹ ti wá rí i pé òótọ́ ni ohun tí Bíbélì ti ń sọ nípa àwọn ọmọdé látìgbà yìí wá, ìyẹn ni pé ó dà bí i pé wọ́n kì í lè ronú bí i ti àgbàlagbà. Bí àpẹẹrẹ, Òwe 22:15 sọ pé: “Ọkàn-àyà ọmọdékùnrin ni ìwà òmùgọ̀ dì sí.” Ọlọ́run sì tún mí sí àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù láti kọ̀wé pé: “Nígbà tí mo jẹ́ ìkókó, mo máa ń . . . ronú bí ìkókó, gbèrò bí ìkókó; ṣùgbọ́n nísinsìnyí tí mo ti wá di ọkùnrin, mo ti fi òpin sí àwọn ìwà ìkókó.”—1 Kọ́ríńtì 13:11.
Kò sí bí ọmọdé kan ṣe lè mọ gbogbo ohun tó wé mọ́ ìbálòpọ̀, ká má ṣẹ̀ṣẹ̀ sọ ohun tó máa tìdí ẹ̀ yọ bọ́jọ́ ṣe ń gorí ọjọ́. Nítorí náà, káàkiri ibi gbogbo làwọn èèyàn ti gbà pé bí wọ́n bá tiẹ̀ bá ọmọdé lò pọ̀, ohun tó ń ṣẹlẹ̀ ò yé e. Ohun tíyẹn túmọ̀ sí ni pé, bí àgbàlagbà kan (tàbí ẹnì kan tó ti bàlágà) bá bá ọmọdé kan lò pọ̀, irú ẹni bẹ́ẹ̀ ò lè dára ẹ̀ láre nípa sísọ pé kíkọ̀ tọ́mọ náà ò kọ̀ ló fà á tàbí kó sọ pé ọmọ náà ló sọ pé òun fẹ́ bẹ́ẹ̀. Àgbàlagbà tó bá dán irú ẹ̀ wò fipá bá ọmọ náà lò pọ̀ ni. Ìwà ọ̀daràn gbáà ló hù yẹn, ó sì máa ṣẹ̀wọ̀n ẹ̀. Òun tó fipá bá ẹlòmíì lò ló máa dáhùn fún un, kì í ṣe ẹni tó jókòó ara ẹ̀ jẹ́jẹ́ tó lọ fipá bá lò.
Àmọ́, ó bani nínú jẹ́ pé ọ̀pọ̀ irú ìwà ọ̀daràn bẹ́ẹ̀ làwọn èèyàn ń ṣe láṣegbé lóde òní. Bí àpẹẹrẹ, nílẹ̀ Ọsirélíà, wọ́n ti fojú bù ú pé ìdá mẹ́wàá péré lára ìdá ọgọ́rùn-ún abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe ni wọ́n ń jẹ́jọ́, díẹ̀ lára wọn nilé ẹjọ́ sì ń dẹ́bi fún. Bí nǹkan sì ṣe rí láwọn ilẹ̀ míì náà nìyẹn. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé kékeré ni ìjọba lè ṣe lára ọ̀ràn náà, fífi ìlànà Bíbélì sílò lè ṣe èyí tó pọ̀ lára ẹ̀ nínú ilé àwọn tó jẹ́ Kristẹni.
Àwọn Kristẹni tòótọ́ mọ̀ pé Ọlọ́run tó mú kí wọ́n kọ àwọn ìlànà wọ̀nyẹn sínú Ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò tíì yí padà. Gbogbo ohun tá à ń ṣe ló ń rí, tó fi mọ́ èyí tó pa mọ́ lójú ọ̀pọ̀ èèyàn. Bíbélì sọ pé: “Ohun gbogbo wà ní ìhòòhò àti ní ṣíṣísílẹ̀ gbayawu fún ojú ẹni tí a óò jíhìn fún.”—Hébérù 4:13.
Àwa la máa dáhùn fún un níwájú Ọlọ́run bá a bá ṣàìgbọràn sí òfin rẹ̀ tá a sì pa àwọn ẹlòmíì lára. Lọ́wọ́ mìíràn ẹ̀wẹ̀, ó máa ń bù kún wa bá a bá ń ṣègbọràn sáwọn òfin wíwúlò tó ṣe nípa bó ṣe yẹ kí nǹkan rí nínú ìdílé. Kí ni díẹ̀ lára àwọn òfin wọ̀nyí?
Ìdílé Tí Ìfẹ́ So Pọ̀ Ṣọ̀kan
Bíbélì sọ fún wa pé: “Ìfẹ́ . . . jẹ́ ìdè ìrẹ́pọ̀ pípé.” (Kólósè 3:14) Gẹ́gẹ́ bí Bíbélì ṣe sọ, ìfẹ́ kì í wulẹ̀ ṣe bí nǹkan kàn ṣe rí lára. Ohun tó máa ń sún èèyàn ṣe la fi ń dá a mọ̀, ìyẹn ni ohun tó máa ń mú kéèyàn hù níwà àti ohun tó máa ń jẹ́ kéèyàn yẹra fún. (1 Kọ́ríńtì 13:4-8) Ohun tí fífi ìfẹ́ hàn nínú ìdílé túmọ̀ sí ni pé kéèyàn máa ṣe ohun tó buyì kún àwọn tó jẹ́ ara ìdílé, kéèyàn máa bọ̀wọ̀ fún wọn, kéèyàn sì máa fi inú rere hàn sí wọn. Ó túmọ̀ sí pé kéèyàn mọ ojú tí Ọlọ́run fi ń wo ẹnì kọ̀ọ̀kan nínú ìdílé, kéèyàn sì máa bá wọn lò lọ́nà bẹ́ẹ̀. Ipò tó lọ́lá tó sì ṣe pàtàkì ni Ọlọ́run to ẹnì kọ̀ọ̀kan sí.
Gẹ́gẹ́ bí olórí ìdílé, bàbá ni kó jẹ́ ẹni àkọ́kọ́ tí yóò máa fi ìfẹ́ hàn. Ó gbọ́dọ̀ mọ̀ pé Ọlọ́run ò fún baba tó jẹ Kristẹni lómìnira pé kó jẹ́ òǹrorò tàbí ẹni tó ń ṣi agbára ẹ̀ lò lórí aya àtàwọn ọmọ ẹ̀. Kàkà bẹ́ẹ̀, ó ń wo Kristi gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tó yẹ kóun máa tẹ̀ lé láti lo ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí. (Éfésù 5:23, 25) Nítorí náà, ó ń fìwà pẹ̀lẹ́ àti ìfẹ́ bá aya rẹ̀ lò, ó sì ń fi sùúrù àti ìwà jẹ́jẹ́ báwọn ọmọ ẹ̀ gbé. Kì í fi ọ̀ràn ààbò wọn ṣeré, kò sì kọ ohun tó lè ná an nítorí àtigbà wọ́n lọ́wọ́ ìjàngbọ̀n, ìyànjẹ, tàbí ohun tí ò ní jẹ́ kí wọ́n lè fọkàn tánni mọ́ àti ohun tó lè wu wọ́n léwu.
Bákan náà sì tún ni ojúṣe ìyàwó, tó sì tún jẹ́ ìyá àwọn ọmọ nínú ilé, ṣe pàtàkì tó sì tún ń buyì kúnni. Bíbélì lo ọgbọ́n àdámọ́ni táwọn ẹranko tó jẹ́ ìyà ní láti fi ṣàpèjúwe bí Jèhófà àti Jésù ṣe máa ń dáàbò boni. (Mátíù 23:37) Bó ṣe yẹ káwọn ìyá tó jẹ́ èèyàn náà máa dáàbò bo àwọn ọmọ wọn lójú méjèèjì nìyẹn. Ìfẹ́ tó bá ní sí wọn á jẹ́ kó tètè máa fi ọ̀ràn ààbò àti ire wọn ṣáájú nínú ohun gbogbo tó bá ń ṣe. Àwọn òbí ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí lílo agbára nílòkulò, bíbúmọ́ni, tàbí kíkó jìnnìjìnnì báni wọ ọ̀rọ̀ àwọn méjèèjì tàbí bí wọ́n ṣe ń bá àwọn ọmọ wọn lò; bẹ́ẹ̀ ni wọn ò sì gbọ́dọ̀ jẹ́ káwọn ọmọ wọn máa fi irú ànímọ́ bẹ́ẹ̀ bára wọn lò.
Bí àwọn tó wà nínú ìdílé bá ń bọ̀wọ̀ fúnra wọn tí wọ́n sì ń buyì fúnra wọn, wọ́n á lè máa bara wọn sọ̀rọ̀ lọ́nà tí ń gbéni ró. Òǹkọ̀wé William Prendergast sọ pé: “Ó yẹ kí gbogbo òbí máa báwọn ọmọ wọn kékeré àtàwọn tó ti bàlágà fikùnlukùn lójoojúmọ́ àti nígbà gbogbo.” Ó fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀ pé: “Ó dà bíi pé ọ̀nà tó dára jù lọ láti gbà yanjú ìṣòro ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe nìyí.” Kódà, irú ìjùmọ̀sọ̀rọ̀ onífẹ̀ẹ́ tó ń wáyé lemọ́lemọ́ yẹn gan-an ni Bíbélì dá lábàá. (Diutarónómì 6:6, 7) Báwọn òbí bá fi ìlànà yìí sílò, ilé á di ibi tí oníkálùkù á ti lè sọ ohun tó bá wà lọ́kàn ẹ̀ fàlàlà àti láìfòyà.
Òótọ́ ni pé inú ayé búburú là ń gbé, kò sì sí béèyàn ṣe lè kòòré gbogbo ìbọ́mọdé-ṣèṣekúṣe. Síbẹ̀, kò sóhun tá a lè fi wé kéèyàn máa gbé nínú ilé tí kò ti sí ewu. Bí ohunkóhun bá pa ẹnikẹ́ni lára níta, ó mọ̀ pé òun nílé tóun lè sá wá, níbi tóun á ti rí ìtùnú tí wọ́n á sì bá òun kẹ́dùn. Ibi ààbò gbáà nirú ilé bẹ́ẹ̀ jẹ́, ibi téèyàn lè forí pa mọ́ sí nínú ayé tó kún fún wàhálà yìí. Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run bù kún ọ bó o ti ń sapá láti mú kí ìdílé tìẹ náà rí bẹ́ẹ̀!
[Àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé]
a Wọ́n tún túmọ̀ ọ̀rọ̀ Gíríìkì àtijọ́ náà báyìí: “Ọlọ́kàn líle sí ìbátan.” Nítorí náà, bó ṣe kà nínú ìtumọ̀ Bíbélì kan nìyí: “Wọ́n á . . . ṣaláìní ìfẹ́ yíyẹ sáwọn ará ilé wọn.”
[Àpótí/Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 10]
ÀWỌN ÀBÁ NÍPA BÍ ÌBỌ́MỌDÉ-ṢÈṢEKÚṢE Ò ṢE NÍ WÁYÉ NÍNÚ ILÉ
Íńtánẹ́ẹ̀tì: Báwọn ọmọ ẹ bá ń lo Íńtánẹ́ẹ̀tì, o gbọ́dọ̀ tọ́ wọn sọ́nà kí wọ́n má bàa ṣì í lò. Àìmọye ibi téèyàn ti lè máa wo àwòrán oníhòòhò ló wà lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì, ìyẹn ò sì mọ́ àwọn ibi ìfọ̀rọ̀wérọ̀ àtàwọn ìkànnì míì táwọn èèyàn ti lè kàn síra wọn. Àwọn abọ́mọdé-ṣèṣekúṣe máa ń wá àwọn ọmọdé lọ sáwọn ibi ìfọ̀rọ̀wérọ̀ orí kọ̀ǹpútà yìí kí wọ́n bàa lè tàn wọ́n kí wọ́n sì bá wọn ṣèṣekúṣe. Ó bọ́gbọ́n mu kí kọ̀ǹpútà náà wà ní gbalasa níbi tá á ti rọrùn fún òbí láti máa bójú tó ìlò rẹ̀. Àwọn ọmọ kò gbọ́dọ̀ fún ẹnikẹ́ni ní ìsọfúnni nípa ara wọn àfi báwọn òbí wọn bá mọ̀ nípa ẹ̀, wọn ò sì gbọ́dọ̀ fìpàdé síbikíbi pẹ̀lú ẹni tí wọ́n bá bá pàdé lórí Íńtánẹ́ẹ̀tì.—Sáàmù 26:4.
Ọtí Líle: Lọ́pọ̀ ìgbà tí ẹnì kan bá bá ọmọdé kan ṣèṣekúṣe, ṣe ló máa ń já sí pé onítọ̀hún ti mutí yó. Ó ti wá hàn kedere báyìí pé àmujù ọtí máa ń sọ àwọn àgbàlagbà di aláìmojú àti aláìmọra; kì í sì í jẹ́ kójú tì wọ́n láti hùwà tí kò tọ́ sí wọn. Lédè kan ṣá, ìyẹn náà tún jẹ́ ọ̀kan lára ìdí tó fi yẹ kéèyàn ṣègbọràn sí ìmọ̀ràn Bíbélì pé ká sá fún àmujù ọtí àti mímutí lámuyó.—Òwe 20:1; 23:20, 31-33; 1 Pétérù 4:3.
Dídá Wà: Obìnrin kan níran ohun tó ṣẹlẹ̀, ó sọ pé: “Lẹ́yìn ikú Màmá mi, iyàrá bàbá mi nìkan ni aṣọ ẹnu-ọ̀nà wà, yàrá wọn nìkan ló sì ní ilẹ̀kùn. Gbayawu làwa yòókù wà, kódà kò sí ilẹ̀kùn níbi tá a ti ń wẹ̀.” Kò sí èyí tí bàbá mi ò bá ṣèṣekúṣe nínú àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin. Torí náà, gbogbo ẹni bá wà nínú ìdílé gbọ́dọ̀ mọ̀ pé gbogbo ìgbà kọ́ lèèyàn máa ń ṣí ara sílẹ̀. Bó ṣe jẹ́ pé ìgbà míì máa ń wà táwọn òbí kì í múra tàbí bọ́ra sílẹ̀ lójú àwọn ọmọ, bẹ́ẹ̀ náà ló yẹ káwọn òbí mọ̀ pé ó láwọn àkókò táwọn ọmọ náà á fẹ́ múra tàbí bọ́ra sílẹ̀, ó sì yẹ káwọn náà ṣe gáfárà fún wọn pàápàá bí wọ́n bá ṣe ń dàgbà sí i. Ohun táwọn òbí tó gbọ́n bá ń retí lọ́dọ̀ ọmọ wọn làwọn náa máa ń ṣe fọ́mọ.—Mátíù 7:12.
-