ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ǹjẹ́ Ó Ní Nǹkan Tí ìrètí Lè Ṣe fún Wa?
    Jí!—2004 | May 8
    • Ǹjẹ́ Ó Ní Nǹkan Tí ìrètí Lè Ṣe fún Wa?

      ỌMỌ ọdún mẹ́wàá péré ni Daniel, àmọ́ ó tó ọdún kan tí àrùn jẹjẹrẹ ti ń bá a fínra. Àwọn oníṣègùn tó ń tọ́jú rẹ̀ àtàwọn èèyàn rẹ̀ ti gba kámú pé ọmọkùnrin yìí ò lè rù ú là. Ṣùgbọ́n Daniel ò sọ̀rètí nù. Ó ní ìgbàgbọ́ pé òun á dàgbà lọ́jọ́ kan, òun á di olùṣèwádìí, òun á sì máa tọ́jú àwọn tó bá lárùn jẹjẹrẹ. Ìrètí tó ń mú inú rẹ̀ dùn ni pé dókítà tó ń wo irú jẹjẹrẹ tó ń ṣe é yẹn máa tó wá wò ó. Àmọ́, nígbà tó dọjọ́ tó yẹ kí dókítà yẹn wá, kò lè wá mọ́ nítorí ojú ọjọ́ tí ò dára. Ọkàn Daniel gbọgbẹ́. Ìgbà àkọ́kọ́ nìyẹn tó máa rọ jọwọrọ sórí bẹ́ẹ̀dì. Ọjọ́ kẹta ló kú.

      Olùtọ́jú aláìsàn kan tó kọ́ nípa bí ìrètí àti àìnírètí ṣe lè nípa lórí ìlera wa ló sọ ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Daniel. Bóyá ni ìwọ náà ò ti gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ rí. Bí àpẹẹrẹ, arúgbó kan wà tí ò lè pẹ́ kú ṣùgbọ́n ó ń retí ọjọ́ pàtàkì kan, bóyá àlejò pàtàkì tó fẹ́ wá kí i ni o tàbí ayẹyẹ kan. Nígbà tọ́jọ́ tó ń retí yẹn pé tó sì lọ, kò pẹ́ tó fi kú. Kí ló mú káwọn ọ̀ràn yẹn rí bẹ́ẹ̀? Àbí ìrètí tiẹ̀ lágbára tó báwọn kan ṣe rò?

      Àwọn olùwádìí nípa ìtọ́jú ìṣègùn tí iye wọn ń pọ̀ sí i ló ń sọ pé ìfojúsọ́nà fún rere, ìrètí, àtàwọn nǹkan ìdùnnú mìíràn ń nípa tó lágbára gan-an lórí ìgbésí ayé àti ìlera ènìyàn. Àmọ́, èrò àwọn olùwádìí ò ṣọ̀kan lórí ọ̀rọ̀ yẹn. Àwọn olùwádìí kan sọ pé àsé tí ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ ò fìdí rẹ̀ múlẹ̀ ni gbogbo irú èrò bẹ́ẹ̀. Wọ́n máa ń fẹ́ sọ pé kò sí nǹkan mìíràn tó ń dá àárẹ̀ síni lára ju àìsàn lọ.

      Kì í ṣòní, kì í ṣàná rèé táwọn kan ti gbà pé ìrètí ò já mọ́ nǹkan kan. Ní ẹgbẹ̀rún ọdún díẹ̀ sẹ́yìn, nígbà tí wọ́n ní kí Aristotle tó jẹ́ onímọ̀ èrò orí Gíríìkì sọ ohun tó ń jẹ́ ìrètí, ó dáhùn pé: “Àlá orí ìrìn ni.” Láìpẹ́ yìí sì rèé, Benjamin Franklin tó jẹ́ àgbà òṣèlú kan lórílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà sọ ọ́ ṣàn-án bó ṣe rí lọ́kàn rẹ̀ pé: “Inú ààwẹ̀ lẹni tó bá jókòó sórí ìrètí máa kú sí.”

      Ó dáa nígbà náà, kí ló ń jẹ́ ìrètí gan-an? Ṣé ríronú pé ohun tó wù wá yóò ṣẹlẹ̀ lásán ni, ìyẹn ọ̀nà téèyàn kàn máa ń gbà láti fi àlá tí ò lè ṣẹ dára rẹ̀ nínú dùn? Àbí ìdí wà tó fi yẹ ká ka ìrètí sí ohun tó jù bẹ́ẹ̀ lọ, ohun tá a gbọ́dọ̀ ní nítorí pé ó ṣe pàtàkì fún ìlera àti ayọ̀ wa àti pé ó jẹ́ ohun tá a nílò, ó sì láǹfààní gidi tó lè ṣe fún wa?

  • Kí Nìdí Tá A Fi Nílò Ìrètí?
    Jí!—2004 | May 8
    • Kí Nìdí Tá A Fi Nílò Ìrètí?

      KÁ NÍ ìrètí Daniel, ọmọkùnrin tó lárùn jẹjẹrẹ tá a sọ̀rọ̀ rẹ̀ níbẹ̀rẹ̀ àpilẹ̀kọ tó ṣáájú èyí ò ṣákìí ni, kí ni ì bá ṣẹlẹ̀? Ǹjẹ́ ì bá ru àrùn jẹjẹrẹ náà là? Ṣé á ṣì wà láàyè dòní? Kódà àwọn tó ń fìgbà gbogbo sọ pé ìrètí lè mú ìwòsàn wá gan-an ò lè fọwọ́ rẹ̀ sọ̀yà. Kókó pàtàkì kan sì nìyẹn jẹ́. Kò yẹ ká pọ́n ìrètí gẹ̀gẹ̀ ju bó ṣe yẹ lọ. Kì í ṣe awogba-àrùn, kì í ṣe gbogboǹṣe.

      Nígbà tí ilé iṣẹ́ ìròyìn CBS fọ̀rọ̀ wá Dókítà Nathan Cherney lẹ́nu wò, ó kìlọ̀ pé ó léwu láti máa pọ́n ìrètí gẹ̀gẹ̀ ju bó ṣe yẹ lọ nígbà tá a bá ń tọ́jú àwọn tí àìsàn wọn le gan-an. Ó sọ pé: “A ti rí àwọn ọkọ tí wọ́n ń bá ìyàwó wọn wí pé wọn kì í ṣe àṣàrò dáadáa àti pé wọn ò lérò tó dáa tó. Ohun tí èrò òdì yìí túmọ̀ sí ni pé ọwọ́ aláìsàn ló wà yálà ó máa tètè gbádùn tàbí kò ní tètè gbádùn, tó bá sì wá di pé ohun tó ń ṣe aláìsàn náà burú sí i, irú bí ìgbà tí jẹjẹrẹ tó wú sára ẹ̀ bá tóbi sí i a jẹ́ pé kò tọ́jú ara rẹ̀ dáadáa nìyẹn. Irú èrò bẹ́ẹ̀ ò sì dára.”

      Ká sòótọ́, ojú àwọn tó ń ṣàìsàn tó la ikú lọ ti rí màbo lọ́wọ́ àìsàn náà. Kò sí ẹbí tàbí ọ̀rẹ́ tá tún fẹ́ pa kún ohun tí wọ́n ń forí rọ́ nípa dídá wọn lẹ́bi. Ṣé a wá lè torí bẹ́ẹ̀ sọ pé ìrètí ò wúlò fún nǹkan kan?

      A ò lè sọ bẹ́ẹ̀ rárá. Iṣẹ́ dókítà kan náà yìí ni láti ran àwọn aláìsàn lọ́wọ́ láti dín ìrora wọn kù—kì í ṣe nípasẹ̀ ìtọ́jú tó lè mú àìsàn náà kúrò tàbí èyí tó lè mú kí ẹ̀mí aláìsàn náà gùn sí i, àmọ́ kó tọ́jú aláìsàn náà káyé lè dẹrùn fún un, kó sì gbádùn ìwọ̀nba tó kù tá lò láyé. Irú àwọn dókítà bẹ́ẹ̀ gbà pé ó ṣeé ṣe láti tọ́jú aláìsàn kí inú rẹ̀ túbọ̀ máa dùn, àní àwọn tí àìsàn wọn le koko pàápàá. Ẹ̀rí jaburata wà pé ìrètí lè ṣe bẹ́ẹ̀, ó sì lè ṣe jù bẹ́ẹ̀ lọ.

      Bí Ìrètí Ṣe Wúlò Tó

      Oníròyìn kan tó máa ń kọ̀ròyìn nípa ìṣègùn, tí orúkọ ìnagijẹ rẹ̀ ń jẹ́ Dókítà W. Gifford-Jones sọ pé: “Ìtọ́jú tó lágbára ni ìrètí.” Ó yẹ oríṣiríṣi ìwádìí tí wọ́n ti ṣe wò láti mọ bó ṣe ṣe pàtàkì tó láti máa ṣaájò àwọn tí àìsàn tó la ikú lọ ń ṣe. Èrò wọn ni pé ṣíṣaájò àwọn èèyàn lọ́nà yìí á ràn wọ́n lọ́wọ́ láti má sọ̀rètí nù, á sì jẹ́ kí wọ́n lérò tó dáa. Ìwádìí kan tí wọ́n ṣe lọ́dún 1989 fi hàn pé ó máa ń pẹ́ kí àwọn aláìsàn tí wọ́n bá rí irú aájò bẹ́ẹ̀ gbà tó kú, bó tilẹ̀ jẹ́ pé a ò rí nǹkan pàtó tó jọ bẹ́ẹ̀ tá a lè rí gbá mú láti inú ìwádìí tí wọ́n ń ṣe lẹ́nu àìpẹ́ yìí. Àmọ́ ṣá, ìwádìí fìdí rẹ̀ múlẹ̀ pé àwọn aláìsàn táwọn èèyàn ṣaájò wọn kì í sábà ní ìdààmú ọkàn àti ìrora bí àwọn táwọn èèyàn pa tì.

      Tún wo ìwádìí mìíràn tí wọ́n ṣe, èyí tó dá lórí ipa tí ẹ̀mí pé nǹkan yóò dára àti ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dára ń ní lórí àrùn tó ń ṣe iṣan tó ń gbẹ́jẹ̀ wọnú ọkàn. Ó lé ní ẹ̀ẹ́dégbèje [1,300] àwọn ọkùnrin tí wọ́n yẹ̀ wò láti mọ̀ bóyá èrò tí wọ́n ní nípa ìgbésí ayé ni ẹ̀mí pé nǹkan yóò dára tàbí pé nǹkan kò ní dáa. Nígbà tí wọ́n tún ìwádìí yẹn ṣe lọ́dún mẹ́wàá lẹ́yìn náà, wọ́n rí i pé ìdá méjìlá nínú ọgọ́rùn-ún lára àwọn ọkùnrin náà ló ti ní àrùn tó ń ṣe iṣan tó ń gbẹ́jẹ̀ wọnú ọkàn rí. Lára gbogbo àwọn ọkùnrin tí wọ́n yẹ̀ wò yìí, àwọn tó gbà pé ara àwọn kò ní yá nínú wọn tó ìlọ́po méjì àwọn tó gbà pé ara àwọn máa yá. Laura Kubzansky, tó jẹ́ igbákejì ọ̀jọ̀gbọ́n nínú ẹ̀kọ́ nípa ìlera àti ìhùwà ẹ̀dá ní Ilé Ẹ̀kọ́ Nípa Ìlera Gbogbo Gbòò ti Harvard, sọ pé: “Àgbọ́sọ lásán ni èyí tó pọ̀ jù lọ nínú àwọn ẹ̀rí tó wà pé ‘ríronú lọ́nà rere’ ṣe pàtàkì fún ìlera rẹ—ìwádìí tí wọ́n ṣe yìí ló jẹ́ ẹ̀rí àkọ́kọ́ tá a ṣẹ̀ṣẹ̀ lè fọwọ́ rẹ̀ sọ̀yà nínú ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ pé ó ṣe pàtàkì, pàápàá lórí àrùn ọkàn.”

      Àwọn ìwádìí kan fi hàn pé àwọn tó gbà pé olókùnrùn làwọn kì í tètè gbádùn lẹ́yìn tí wọ́n bá ṣe iṣẹ́ abẹ fún wọn bí àwọn tó gbà pé ara àwọn le dáadáa. Kódà, wọ́n tiẹ̀ sọ pé béèyàn bá lẹ́mìí pé nǹkan yóò dáa, ó lè pẹ́ láyé. Wọ́n ṣe ìwádìí lórí ipa tí ojú táwọn èèyàn fi ń wo ọjọ́ ogbó ń ní lórí àwọn arúgbó. Nígbà tí wọ́n jẹ́ káwọn arúgbó gbọ́ ọ̀pọ̀ nǹkan táwọn èèyàn ń sọ nípa bí ọgbọ́n àti ìrírí ṣe máa ń pọ̀ béèyàn ṣe ń darúgbó, àwọn arúgbó yìí lókun àti agbára láti rìn kánmọ́kánmọ́ sí i. Àní, ńṣe ló dà bíi pé wọ́n fi ọ̀sẹ̀ méjìlá ṣe eré ìmárale tó fún wọn lágbára!

      Kí ló dé tó fi dà bí i pé ìrètí, ẹ̀mí pé nǹkan yóò dáa àti èrò rere ṣàǹfààní fún ìlera? Bóyá làwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀ àtàwọn dókítà lóye èrò inú àti ara èèyàn débi tí wọ́n á fi lè dáhùn irú ìbéèrè yìí ṣàkó. Síbẹ̀, àwọn ògbógi tí wọ́n kọ́ nípa ìrònú àti ara èèyàn lè máa méfò látàrí ohun tí wọ́n kọ́ àti ìrírí wọn. Bí àpẹẹrẹ, ọ̀jọ̀gbọ́n kan nínú ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa ètò iṣan ara sọ pé: “Inú dídùn máa ń mórí yá, àgbẹ́kẹ̀lé kì í sì í pani lébi. Báyọ̀ bá gbọkàn èèyàn ìdààmú ò ní sí lọ́kàn olúwarẹ̀ bẹ́ẹ̀ sì lara èèyàn máa ń balẹ̀. Ara nǹkan téèyàn lè ṣe láti jẹ́ kára òun máa jí pépé ni kó máa wá bí inú òun yóò ṣe máa dùn.”

      Ohun tá à ń sọ yìí lè dà bí àrà tuntun lójú àwọn dókítà, afìṣemọ̀rònú ẹ̀dá àtàwọn onímọ̀ ìjìnlẹ̀, ṣùgbọ́n lójú àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì àgbọ̀nrín èṣí ni. Ó ti tó ẹgbẹ̀ẹ́dógún [3,000] ọdún báyìí tí Ọlọ́run ti mí sí ọlọgbọ́n Ọba Sólómọ́nì láti kọ èrò yìí sílẹ̀ pé: “Ọkàn-àyà tí ó kún fún ìdùnnú ń ṣe rere gẹ́gẹ́ bí awonisàn, ṣùgbọ́n ẹ̀mí tí ìdààmú bá ń mú kí àwọn egungun gbẹ.” (Òwe 17:22) Kíyè si pé ọ̀rọ̀ tó wà níbí yìí ò lábùmọ́ o. Ẹsẹ yìí ò sọ pé ọkàn tó kún fún ìdùnnú yóò wo àìsàn kankan o, ṣùgbọ́n ó sọ pé ó “ń ṣe rere gẹ́gẹ́ bí awonisàn.”

      Kò burú tẹ́nìkan bá béèrè pé, Bó bá jẹ́ pé oògùn ni ìrètí, oníṣègùn wo ni kò ní máa júwe ẹ̀ fáwọn èèyàn? Ìrètí tún láwọn àǹfààní mìíràn tó ń ṣe ju mímúniláradá lọ.

      Ipa Tí Irú Ẹ̀mí Tó O Ní Lè Ní Lórí Rẹ

      Àwọn olùwádìí ti rí i pé àwọn tó máa ń lérò pé nǹkan yóò dáa máa ń jàǹfààní lọ́pọ̀lọpọ̀ ọ̀nà látinú èrò wọn. Ó dà bíi pé wọ́n máa ń fakọyọ nílé ìwé, lẹ́nu iṣẹ́, àti nínú eré ìdárayá pàápàá. Bí àpẹẹrẹ, nínú ìwádìí kan, wọ́n ní káwọn obìnrin tí wọ́n wà nínú ẹgbẹ́ eléré ìdárayá kan wá ṣe oríṣiríṣi ìdíje. Àwọn olùkọ́ ẹgbẹ́ eléré ìdárayá náà sọ ibi tí agbára àwọn obìnrin yẹn mọ láti díje nínú eré ìdárayá. Lọ́wọ́ kan náà, wọ́n yẹ àwọn obìnrin náà wò dáadáa wọ́n sì fẹ́ mọ bí ìrètí wọn láti pegedé ṣe lágbára tó. Ẹ jẹ́ mọ̀ pé ìrètí táwọn obìnrin wọ̀nyẹn ní pé àwọn lè pegedé ràn wọ́n lọ́wọ́ ju báwọn olùkọ́ wọn ṣe sọ pé agbára wọn láti díje mọ. Kí nìdí tí ìrètí fi nípa tó lágbára bẹ́ẹ̀ lórí àwọn èèyàn?

      Ọ̀pọ̀ nǹkan laráyé ti kọ́ nípa ìdàkejì ẹ̀mí pé nǹkan yóò dára, ìyẹn ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa. Láàárín ọdún 1960 sí 1970, wọ́n rí ọ̀pọ̀ nǹkan tí wọn ò rò tẹ́lẹ̀ nínú ìwádìí tí wọ́n ṣe nípa báwọn ẹranko ṣe ń hùwà, èyí ló sì sún àwọn olùṣèwádìí láti ṣẹ̀dá ọ̀rọ̀ náà “kíkọ́ àìnírètí.” Wọ́n rí i pé irú àmódi bẹ́ẹ̀ lè kọlu èèyàn pẹ̀lú. Bí àpẹẹrẹ, wọ́n fi àwọn èèyàn kan ṣe ìwádìí, wọ́n kó àwọn wọ̀nyí síbi tí ariwo tó ń han wọ́n létí wà, wọ́n sì sọ fún wọn pé wọ́n lè kọ́ bí wọ́n á ṣe dá ariwo yẹn dúró nípa títẹ àwọn nǹkan kan lára ẹ̀rọ tó ń pariwo náà. Wọ́n rí ariwo yẹn dá dúró.

      Wọ́n kó àwọn mìíràn jọ, wọ́n ní káwọn náà ṣe ohun kan náà, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀ ariwo yẹn ò mà dúró o. Kò lè ṣòro fún ọ láti rí i pé ọ̀pọ̀ lára àwọn kejì yẹn á máa wo ara wọn bí ẹni tí kò ní ìrètí. Nígbà tí wọ́n tún dán wọn wò láìpẹ́ sígbà yẹn, wọn ò tiẹ̀ fẹ́ láti dá ariwo náà dúró. Ìgbàgbọ́ wọn ni pé kò sí nǹkan táwọn lè ṣe tó lè dá ariwo náà dúró. Síbẹ̀, àwọn tó lẹ́mìí pé nǹkan yóò dáa lára wọn pàpà gbà pé ariwo yẹn lè dúró, wọn ò gbà pé àwọn ò ní ìrètí.

      Ọ̀mọ̀wé Martin Seligman, tó bá wọn ṣètò ìwádìí yẹn kúkú torí bẹ́ẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí kẹ́kọ̀ọ́ nípa ẹ̀mí pé nǹkan yóò dáa àti ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa. Ó wá fìn-ín ìdí kókò nípa báwọn tó gbà pé àwọn ò nírètí ṣe máa ń ronú. Ó sọ pé irú èrò pé nǹkan kò ní dára bẹ́ẹ̀ máa ń ṣèdíwọ́ fáwọn tó bá ní in bí wọ́n bá fẹ́ gbé nǹkan ṣe nínú ìgbésí ayé, kódà ó lè sọ wọ́n di aláìlè dá nǹkan kan ṣe. Seligman wá fi gbólóhùn kan kó gbogbo ipa tí ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa máa ń ní pọ̀, ó ní: “Láàárín ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n tí mo fi kẹ́kọ̀ọ́, ó ti dá mi lójú pé tá a bá sábà ń ní irú èrò táwọn tó ní ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa máa ń ní, ìyẹn èrò pé ẹ̀bi wa ni ìṣòro tó bá dé bá wa, àti pé kò ní lọ, tá sì máa dabarú gbogbo nǹkan tá a bá dáwọ́ lé, bẹ́ẹ̀ náà ni ìṣòro á máa ṣẹlẹ̀ sí wa tó.”

      Gẹ́gẹ́ bá a ṣe sọ ṣáájú, ó lè jọ àwọn kan lójú pé ìrètí lágbára tó bẹ́ẹ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe ọ̀rọ̀ tuntun létí àwọn akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Òwe yìí wà nínú Bíbélì pé: “Ìwọ ha ti jẹ́ kí ìrẹ̀wẹ̀sì bá ọ ní ọjọ́ wàhálà bí? Agbára rẹ yóò kéré jọjọ.” (Òwe 24:10) Òdodo ọ̀rọ̀, Bíbélì ṣàlàyé kedere pé ìrẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú èrò òdì tó máa ń bá a rìn lè gba agbára lọ́wọ́ rẹ tó ò sì ní lè dá nǹkan ṣe mọ́. Ṣùgbọ́n kí lo lè ṣe láti kòòré ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa, tí wà á wá dẹni tó lérò pé nǹkan yóò dára, tí wà á sì nírètí?

      [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 14, 15]

      Ìrètí lè ṣe ọ́ láǹfààní tó kọ yọyọ

  • O Lè Gbara Rẹ Lọ́wọ́ Ẹ̀mí Pé Nǹkan Ò Ní Dára
    Jí!—2004 | May 8
    • O Lè Gbara Rẹ Lọ́wọ́ Ẹ̀mí Pé Nǹkan Ò Ní Dára

      OJÚ wo lo fi máa ń wò ó, bí ọ̀nà ò bá gba ibi tó o fojú sí? Ọ̀pọ̀ àwọn ògbógi gbà pé ohun tó máa pinnu ìdáhùn sí ìbéèrè yẹn ni irú ẹ̀mí tó o ní. Gbogbo wa pátá la ní ibi tí bàtà ti ń ta wá lẹ́sẹ̀, ìṣòro wa kàn jura lọ ni. Kí ló wá dé tó fi dà bí i pé àwọn kan máa ń tètè borí ìṣòro tó ń bá wọn fínra tí wọ́n á sì túnra mú, nígbà tó jẹ́ pé káwọn míì máà tíì rí ìṣòro ni, wọ́n ti pa ohun tí wọ́n ń ṣe tì?

      Bí àpẹẹrẹ, ká sọ pé ò ń wáṣẹ́. O lọ síbi tí wọ́n ti fọ̀rọ̀ wá àwọn tí wọ́n fẹ́ gbà lẹ́nu wò, àmọ́ iṣẹ́ náà ò bọ́ sí ọ lọ́wọ́. Kí ni wàá rò pé kò jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́? O lè rò pé ìwọ gan-an ni wọn ò fẹ́, kó o sì wá máa rò pé ìṣòro tí wàá máa gbé kiri nìyẹn, kó o wá máa sọ fúnra rẹ pé, ‘Kò sẹ́ni tá fẹ́ gba irú mi yìí síṣẹ́. Mi ò tiẹ̀ lè ríṣẹ́ ni.’ Èyí tó tún wá burú jù ni pé o lè wá tìtorí àmúbọ́ ẹ̀ẹ̀kan ṣoṣo yìí ro ara rẹ pin nínú gbogbo ohun tó o bá dáwọ́ lé kó o máa ronú pé, ‘Kò sí nǹkan kan tí mo lè ṣe yọrí. Mi ò wúlò fún ẹnì kankan.’ Gbogbo ìgbà tó o bá ti ń ronú bẹ́ẹ̀, mọ̀ pé ẹ̀mí pé nǹkan ò lè dáa lo ní yẹn.

      Bó O Ṣe Lè Gbara Rẹ̀ Lọ́wọ́ Ẹ̀mí Pé Nǹkan Ò Ní Dáa

      Báwo lo ṣe lè gbara ẹ lọ́wọ́ ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa? Ìgbésẹ̀ pàtàkì àkọ́kọ́ tó yẹ kó o gbé ni pé kó o mọ̀ bí èrò bẹ́ẹ̀ bá ti ń sọ sí ọ lọ́kàn. Lẹ́yìn náà kó o tètè lé e jáde kúrò lọ́kàn rẹ. Ronú ohun mìíràn tó mọ́gbọ́n dání tó lè fà á tọ́wọ́ rẹ kò fi tẹ ohun tó ò ń lé. Bí àpẹẹrẹ, ṣé lóòótọ́ ni pé nítorí pé ẹnikẹ́ni ò ní gbà ọ́ síṣẹ́ ni wọn ò ṣe gbà ọ́? Ṣé kò lè jẹ́ pé wọ́n kàn ń fẹ́ ẹlòmíràn tó ní irú ìwé ẹ̀rí tí ìwọ ò ní ni?

      Tó o bá ro gbogbo bọ́ràn ṣe rí gan-an látòkèdélẹ̀, wàá rí i pé ohun tó ń ṣẹlẹ̀ gan-an ò burú tó bó o ṣe ń rò ó. Ṣé kíkọ̀ tí wọ́n kọ̀ ọ́ níbì kan ti wá fi hàn pé o kò wúlò fún nǹkan míì mọ́ láyé, o ò ṣe ronú nípa àwọn apá ibòmíì tó o ti ń kẹ́sẹ járí nínú ìgbésí ayé rẹ, irú bí àwọn nǹkan tó o dáwọ́ lé nípa tẹ̀mí, àjọṣe rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlòmíì, tàbí pẹ̀lú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ? Mọ ọ̀nà tí wàá fi máa gbé èròkerò kúrò lọ́kàn rẹ, kó o máa wò ó bí ìgbà téèyàn “bá kàn ń kú sílẹ̀ kí ikú tó dé.” Ṣé o tiẹ̀ lè mọ̀ lóòótọ́ pé o kò ní ríṣẹ́ láé ni? Ọ̀pọ̀ nǹkan lo lè ṣe láti gbara ẹ lọ́wọ́ èrò òdì.

      Èrò Tó Dára Tí Ń Múni Ṣàṣeyọrí

      Láwọn ọdún ẹnu àìpẹ́ yìí, àwọn olùwádìí ti wá ọ̀nà mìíràn tí wọ́n á gbà máa ṣàlàyé ohun tó ń jẹ́ ìrètí bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìtumọ̀ tí wọ́n fún un ò gbòòrò tó. Wọ́n ní ohun tó ń jẹ́ ìrètí ni ìgbàgbọ́ pé ọwọ́ rẹ yóò tẹ àwọn ohun tó ò ń lé. A ó rí i nínú àpilẹ̀kọ tó tẹ̀ lé èyí pé ohun tó ń jẹ́ ìrètí ju bí wọ́n ṣe ṣàlàyé rẹ̀ yẹn lọ fíìfíì, àmọ́ ó tún láwọn ibì kan tá a ti lè lo ìtumọ̀ náà. Tá a bá ti apá ibẹ̀ yẹn wo ìrètí wa lẹ́nì kọ̀ọ̀kan a lè ní èrò tó dára tá sì múni ṣàṣeyọrí.

      Ká tó lè gbà gbọ́ pé ọwọ́ wa á tẹ àwọn ohun tá à ń lépa, ó yẹ kó ti mọ́ wa lára láti máa lépa ohun kan kọ́wọ́ wa sì máa tẹ̀ ẹ́. Tó o bá rí i pé ọ̀ràn tìẹ ò rí bẹ́ẹ̀, a dáa kó o tètè rò ó dáadáa kó o tó bẹ̀rẹ̀ sí lépa ohun kan. Dúró ná, ǹjẹ́ ohun kan tiẹ̀ wà tó ò ń lé? Tá à bá ṣọ́ra, làálàá kòókòó ìgbésí ayé lè gba gbogbo àkókò wa débi pé a ò ní lè ráyè ronú lórí ohun tá a fẹ́ gan-an nínú ìgbésí ayé, ìyẹn ohun tó jẹ wá lógún jù lọ. Tipẹ́tipẹ́ ni Bíbélì ti sọ̀rọ̀ lórí ìlànà pàtàkì yìí pẹ̀lú, ìyẹn pé ká máa ní ohun àkọ́múṣe, ó sọ pé: “Ẹ . . . máa wádìí dájú àwọn ohun tí ó ṣe pàtàkì jù.”—Fílípì 1:10.

      Tá a bá ti ní àwọn ohun tá a kọ́kọ́ fẹ́ gbé ṣe, á wá rọrùn sí i láti pinnu àwọn ohun tó ṣe pàtàkì fún wa nínú ìgbésí ayé, bí àpẹẹrẹ, àwọn nǹkan tẹ̀mí, ọ̀ràn tó jẹ mọ́ ìdílé àti iṣẹ́ oúnjẹ òòjọ́ wa. Àmọ́ o, ó ṣe pàtàkì pé ká má ṣe kó irin púpọ̀ bọná lẹ́ẹ̀kan náà, ká sì rí i pé kì í ṣe ohun tápá ò ní ká là ń lépa. Tó bá jẹ́ pé nǹkan tá ṣòro fún wa láti bá la gbé síwájú ara wa, ọkàn wa ò ní balẹ̀, kò sì ní pẹ́ sú wa. Nítorí náà, á dára ká dín àwọn ohun tá à ń lépa kù sí èyí tọ́wọ́ wa á tètè bà, tá ó sì lè máa ṣe díẹ̀díẹ̀.

      Òwe àtijọ́ kan sọ pé: “Àyè kì í há adìyẹ kó máà dé ìdí àba rẹ̀.” Ó sì dà bí i pé òótọ́ díẹ̀ wà nínú òwe yẹn. Tá a bá ti ní àwọn ohun kan lọ́kàn tá a fẹ́ gbé ṣe, ohun tó kù wá kù láti lè bá a ni ìpinnu, ìyẹn ìfẹ́ àtọkànwá àti ìmúratán tá jẹ́ ká lè jára mọ́ ohun tá à ń ṣe. A lè jẹ́ kí ìpinnu wa lágbára sí i tá a bá ronú lórí bí ohun tá à ń lépa ti ṣe pàtàkì tó àtàwọn àǹfààní tá a máa rí níbẹ̀ tọ́wọ́ wa bá tẹ̀ ẹ́. Ìṣòro ò ní ṣaláì sí o, ṣùgbọ́n ṣe ló yẹ ká máa wò wọ́n bí ọ̀pákùtẹ̀lẹ̀ fún ìtẹ̀síwájú dípò ká máa kà wọ́n sí ibodè wáàsinmi.

      Àmọ́ ṣá, ó yẹ ká tún ronú ọ̀nà tọ́wọ́ wa ó fi máa tẹ àwọn ohun tá a bá ń lépa. Òǹkọ̀wé C. R. Snyder, ẹni tó ti ṣe ìwádìí jinlẹ̀ lórí ìwúlò ìrètí, sọ pé ó yẹ ká máa wá oríṣiríṣi ọ̀nà tọ́wọ́ wa ó fi máa tẹ àwọn ohun tá a bá ń lépa. Ìyẹn á lè jẹ́ ká yẹ ọ̀nà mìíràn wò bí ọ̀nà kan bá dí, nítorí pé ọ̀nà kan ò wọjà.

      Snyder tún dábàá pé ó yẹ ká kọ́ bá a ṣe ń fi ìkan dí ìkan. Tó bá di pé ohun tá à ń lépa fẹ́ bọ́ rẹ́lẹ̀, dídààmú nípa rẹ̀ á wulẹ̀ mú ká rẹ̀wẹ̀sì ni. Àmọ́, tá a bá fi ìlépa mìíràn tí ò pọ̀ jura lọ rọ́pò rẹ̀, a óò lè ní ohun mìíràn tí yóò máa fún wa nírètí.

      Àpẹẹrẹ kan wà nínú Bíbélì tá jẹ́ kí ohun tá à ń sọ yìí yé wa yékéyéké. Ó wu Ọba Dáfídì bíi kó kọ́ tẹ́ńpìlì fún Jèhófà, Ọlọ́run rẹ̀. Àmọ́, Ọlọ́run sọ fún Dáfídì pé Sólómọ́nì ọmọkùnrin rẹ̀ ló máa láǹfààní àtikọ́ ọ. Kàkà kí Dáfídì wá kárí sọ tàbí kó kàn máa ṣe kìràkìtà nídìí àléèbá, ńṣe ló dáwọ́ lé àwọn nǹkan míì. Ó lo gbogbo agbára ẹ̀ láti kó owó àti gbogbo ohun èlò tí ọmọ rẹ̀ máa nílò láti parí iṣẹ́ ilé náà jọ.—1 Àwọn Ọba 8:17-19; 1 Kíróníkà 29:3-7.

      Kódà, tá a bá ti bá a débi tí ìrètí wa ti lágbára láti borí ẹ̀mí pé nǹkan ò ní dáa, tá a sì ti wá lérò tó dára, tó lè múni ṣàṣeyọrí pàápàá, ó tún ṣì lè dà bí ẹni pé àìnírètí ń dà wá láàmú. Kí ló lè fà á? Ohun tó wà níbẹ̀ ni pé ọ̀pọ̀ nǹkan tó ń fa àìnírètí láyé yìí kọjá àwọn nǹkan tí agbára wá lè ká pátápátá. Tá a bá wá ronú nípa àwọn àrágbá yamúyamù ìṣòro tó ń gbo aráyé mọ́lẹ̀ yìí, ìyẹn àwọn bí òṣì, ogun, àìsídàájọ́ òdodo àti bí ikú òun àrùn ṣe ń fẹjú mọ́ wa, báwo la ṣe lè ní èrò tó dára lọ́kàn?

      [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 17]

      Bí wọn ò bá gbà ọ́ níbi iṣẹ́ kan, ṣé o máa ń ro ara rẹ pin pé o ò lè ríṣẹ́ mọ́?

      [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 18]

      Ọba Dáfídì térò rẹ̀ pa nígbà tó dọ̀rọ̀ pípinnu ohun tó máa ṣe

  • Ibo Lo Ti Lè Rí Ìrètí Tòótọ́?
    Jí!—2004 | May 8
    • Ibo Lo Ti Lè Rí Ìrètí Tòótọ́?

      AAGO ọwọ́ rẹ ti dákẹ́, ó sì dà bí i pé ojú rẹ̀ ti fọ́. Nígbà tó o wá fẹ́ tún un ṣe, o ò mọ ẹni tó ò bá gbé e fún. Ọ̀pọ̀ àwọn tó ń tún aago ṣe ló ń polówó, gbogbo wọn sì ń dánnu mọ́ iṣẹ́ ọwọ́ wọn pé àwọn làwọn lè tún un ṣe, ọ̀rọ̀ wọn ò sì dọ́gba. Ṣùgbọ́n bó o bá wá mọ̀ lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn pé aládùúgbò rẹ kan ni ọ̀jáfáfá tó ṣe aago yẹn lọ́dún mélòó kan sẹ́yìn ńkọ́? Yàtọ̀ sí ìyẹn, o tún gbọ́ pé á bá ọ tún un ṣe lọ́fẹ̀ẹ́, láìgba kọ́bọ̀. Láìdéènà pẹnu, nǹkan tó o máa ṣe á ti yé ọ, àbí bẹ́ẹ̀ kọ́?

      Fi bọ́ràn aago yẹn ṣe rí lára rẹ wé ọ̀ràn ìrètí. Bó o bá rí i pé o ti ń sọ̀rètí nù, bíi tàwọn mìíràn nínú ayé onídààmú yìí, ibo lo lè wá ìrànlọ́wọ́ lọ? Àwọn tó láwọn lè yanjú ìṣòro yẹn lè tó ẹgbàágbèje o, ṣùgbọ́n àìmọye ìmọ̀ràn tí wọ́n ń mú wá ló lè ki orí ẹni bọgbó, bẹ́ẹ̀ ni ìmọ̀ wọn ò ṣọ̀kan. Láìṣe méní méjì, o ò ṣe kúkú forí lé ọ̀dọ̀ Ẹni tó ṣẹ̀dá aráyé lọ́nà tá a fi lè nírètí? Bíbélì sọ fún wa pé “kò jìnnà sí ẹnì kọ̀ọ̀kan wa” ó sì ń retí wa, ó ṣe tán láti ràn wá lọ́wọ́.—Ìṣe 17:27; 1 Pétérù 5:7.

      Ohun Tí Ìrètí Túmọ̀ sí Gan-an

      Bí Bíbélì ṣe ṣàlàyé ohun tó ń jẹ́ ìrètí gbòòrò, ó sì jinlẹ̀ ju báwọn dókítà, onímọ̀ ìjìnlẹ̀ àtàwọn afìṣemọ̀rònú ẹ̀dá ṣe ń fẹnu yẹpẹrẹ ṣàlàyé rẹ̀ lóde òní lọ. Nínú èdè tí wọ́n fi kọ Bíbélì ní ìpilẹ̀sẹ, ìtumọ̀ àwọn ọ̀rọ̀ tí wọ́n túmọ̀ sí “ìrètí” ni pé kéèyàn máa fi ìháragàgà dúró de nǹkan kó sì máa retí ohun tó dára. Ohun pàtàkì méjì ló wà nínú ìrètí. Àwọn ni ìfẹ́ àtọkànwá fún nǹkan tó dára àti ìdí tá a fi lè retí pé ohun tó dára yóò wá. Ìrètí tí Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ kì í kàn ṣe ríronú pé ohun tó wù wá á ṣẹlẹ̀ lásán. A ní ìdí àtí ẹ̀rí tó ṣe gúnmọ́ tá a fi lè rò pé bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ máa rí.

      Ibi tí ìrètí fi jọ ìgbàgbọ́ nìyẹn, orí ẹ̀rí la sì gbọ́dọ̀ gbé e kà, a ò gbọ́dọ̀ gbé e ka orí ìgbàgbọ́ oréfèé. (Hébérù 11:1) Síbẹ̀, Bíbélì sọ ìyàtọ̀ tó wà láàárín ìrètí àti ìgbàgbọ́.—1 Kọ́ríńtì 13:13.

      Bí àpẹẹrẹ: Bó o bá sọ fún ọ̀rẹ́ minú rẹ kan pé kó ṣèrànlọ́wọ́ kan fún ọ, o lè nírètí pé yóò ràn ọ́ lọ́wọ́. O kò ṣàdédé nírú ìrètí bẹ́ẹ̀, nítorí pé o ní ìgbàgbọ́ nínú ọ̀rẹ́ rẹ ni, ìyẹn ni pé o mọ̀ ọ́n dáadáa, o sì ti mọ̀ tẹ́lẹ̀ pé onínúure àti ọlọ́làwọ́ ni. Ìgbàgbọ́ rẹ àti ìrètí rẹ jọ ń rìn ni, kódà wọ́n wọnú ara wọn, ṣùgbọ́n wọ́n yàtọ̀ síra. Báwo lo ṣe lè ní irú ìrètí bẹ́ẹ̀ nínú Ọlọ́run?

      Ìdí Tó O Fi Lè Ní Ìrètí

      Ọlọ́run lorísun ìrètí tòótọ́. Láyé ìgbà tí wọ́n kọ Bíbélì, Jèhófà ni wọ́n ń pè ní “ìrètí Ísírẹ́lì.” (Jeremáyà 14:8) Nítorí náà, ìrètí èyíkéyìí tó ṣeé gbára lé táwọn èèyàn rẹ̀ ní wá látọ̀dọ̀ rẹ̀, fún ìdí èyí, òun ló jẹ́ ìrètí wọn. Irú ìrètí bẹ́ẹ̀ kì í kàn ṣe ohun téèyàn fẹ́ kó ṣẹlẹ̀ nìkan. Ọlọ́run fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ní ìdí tó lágbára tí wọ́n fi lè nírètí. Láti ọ̀pọ̀ ọ̀rúndún tó ti ń bá wọn lò, wọ́n ti rí, wọ́n sì ti gbọ́ bó ṣe mú gbogbo ìlérí tó ṣe ṣẹ. Jóṣúà, tó jẹ́ aṣáájú wọn sọ fún wọn pé: “Ẹ̀yin sì mọ̀ dáadáa . . . pé kò sí ọ̀rọ̀ kan tí ó kùnà nínú gbogbo ọ̀rọ̀ rere tí Jèhófà Ọlọ́run yín sọ fún yín.”—Jóṣúà 23:14.

      Títí di ọ̀pọ̀ ẹgbẹ̀rún ọdún lẹ́yìn ìgbà yẹn, Jèhófà ṣì ń mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ. Ọ̀pọ̀ ìlérí pípabanbarì tí Ọlọ́run ṣe àti bó ṣe mú wọn ṣẹ wà lákọọ́lẹ̀ pípé pérépéré nínú Bíbélì. Ìmúṣẹ àwọn ìlérí tó ṣe dájú tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ débi pé nígbà míì a máa ń kọ wọ́n bíi pé wọ́n ti ní ìmúṣẹ nígbà tó ṣèlérí náà ni.

      Ìdí rèé tá a fi lè pe Bíbélì ní ìwé ìrètí. Bó o bá ṣe ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa bí Ọlọ́run ṣe ń bá àwọn èèyàn lò, bẹ́ẹ̀ ni ìdí tó o ní fún fífi ìrètí rẹ sínú rẹ̀ á ṣe máa lágbára sí. Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù kọ̀wé pé: “Gbogbo ohun tí a ti kọ ní ìgbà ìṣáájú ni a kọ fún ìtọ́ni wa, pé nípasẹ̀ ìfaradà wa àti nípasẹ̀ ìtùnú láti inú Ìwé Mímọ́, kí a lè ní ìrètí.”—Róòmù 15:4.

      Kí Ni Ọlọ́run Fẹ́ Ká Máa Retí?

      Ìgbà wo la nílò ìrètí jù lọ? Ṣé kì í ṣe ìgbà tí ikú bá dojú kọ wá ni? Fún ọ̀pọ̀ èèyàn, nírú àkókò báyẹn gan-an—bóyá nígbà tí ikú bá pa ẹnì kan tó sún mọ́ wọn—ni ìrètí á wá dàwátì. Àbí, kí ló tún kù téèyàn lè ṣe lórí ọ̀rọ̀ ẹni tó ti kú? Bẹ́ẹ̀ sì rèé, gbogbo wa la ti jẹ gbèsè ikú. Kò sí bá a ṣe lè sá fún un tó, ọjọ́ tíkú bá dé kò sí àbùjá lọ́rùn ọ̀pẹ. Wẹ́kú lórúkọ tí Bíbélì pè é bá a mu, ìyẹn “ọ̀tá ìkẹyìn.”—1 Kọ́ríńtì 15:26.

      Nígbà náà, báwo wá la ṣe lè nírètí tíkú bá dé? Tóò, ẹsẹ Bíbélì tó pe ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn yẹn náà tún sọ pé ọ̀tá yìí la ó “sọ di asán.” Jèhófà Ọlọ́run lágbára ju ikú lọ. Kì í ṣòní kì í ṣàná rèé tó ti ń fàjùlọ hàn án. Bíi báwo? Nípa jíjí tó ń jí òkú dìde ni. Bíbélì ròyìn pé ẹ̀ẹ̀mẹsàn-án ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni Ọlọ́run lo agbára rẹ̀ láti sọ àwọn òkú di alààyè.

      Ọ̀kan tó pabanbarì ni ìgbà tí Jèhófà fún Jésù Ọmọ rẹ̀ lágbára láti jí ọ̀rẹ́ rẹ̀ ọ̀wọ́n, Lásárù tó ti kú fún ọjọ́ mẹ́rin dìde. Kọ̀rọ̀ kọ́ ni Jésù ti ṣe èyí, gbangba níṣojú gbogbo ayé ni.—Jòhánù 11:38-48, 53; 12:9, 10.

      O lè máa rò ó pé, ‘Kí ló dé tá a tún fi jí àwọn èèyàn dìde? Ṣebí wọ́n ṣáà pàpà darúgbó tí wọ́n sì kú, àbí wọ́n ṣì wà dòní?’ Wọ́n kú lóòótọ́. Síbẹ̀, nítorí àkọsílẹ̀ tó ṣeé gbára lé nípa àjíǹde, irú bí ìwọ̀nyí, a lè ní kọjá ìfẹ́ ọkàn pé àwọn ẹni tá a fẹ́ràn tí wọ́n kú yóò jíǹde; a ní ìdí láti gbà gbọ́ pé wọ́n á jíǹde. Lédè mìíràn, a lè sọ pé a ní ìrètí tó yanran-n-tí.

      Jésù sọ pé: “Èmi ni àjíǹde àti ìyè.” (Jòhánù 11:25) Òun ni Jèhófà máa fún lágbára láti jí àwọn òkú dìde jákèjádò ayé. Jésù sọ pé: “Wákàtí náà ń bọ̀, nínú èyí tí gbogbo àwọn tí wọ́n wà nínú ibojì ìrántí yóò gbọ́ ohùn [Kristi], wọn yóò sì jáde wá.” (Jòhánù 5:28, 29) Kò sírọ́ ńbẹ̀, gbogbo àwọn tó ń sùn nínú ibojì ló ṣeé ṣe fún láti jíǹde sínú párádísè lórí ilẹ̀ ayé.

      Bí wòlíì Aísáyà ṣe ṣàpèjúwe àjíǹde yìí wúni lórí gan-an ni, ó sọ pé: “Àwọn òkú rẹ yóò yè, . . . wọn ó dìde. Ẹ jí, ẹ sì kọrin, ẹ̀yin tí ń gbé inú ekuru: torí ìrì rẹ ìrì ewébẹ̀ ni, ilẹ̀ yóò si sọ àwọn òkú jáde.”—Aísáyà 26:19, Bibeli Mimọ.

      Ṣé ìyẹn ò tó tu èèyàn nínú? Kò sí ibi tó tún láàbò ju ibi táwọn òkú wà lọ, àfi bí ọmọ inú oyún tí ò sí nǹkan tó ń dà á láàmú nínú ọlẹ̀ ìyá rẹ̀. Àní, àwọn tó ń sinmi nínú ibojì wà nípamọ́ nínú ìrántí Ọlọ́run Olódùmarè, adánimágbàgbé. (Lúùkù 20:37, 38) Kò sì ní pẹ́ mọ́ tí wọ́n á fi padà sí ìyè, wọ́n á jíǹde sínú ayé tá ó ti kí wọn káàbọ̀ bí tẹbí tará ṣe máa ń kí ọmọ tuntun ní àríjó àríyọ̀! Nítorí náà, ìrètí ṣì wà fẹ́ni tó kú pàápàá.

      Ohun Tí Ìrètí Lè Ṣé fún Ọ

      Pọ́ọ̀lù kọ́ wa ní ohun tó pọ̀ nípa àǹfààní tó wà nínú ìrètí. Ó ka ìrètí kún ọ̀kan pàtàkì lára ìhámọ́ra ogun tẹ̀mí, ó pè é ní àṣíborí. (1 Tẹsalóníkà 5:8) Kí nìdí tí Pọ́ọ̀lù fi fi ìrètí wé àṣíborí? Tóò, láyé ìgbà tí wọ́n ń kọ Bíbélì, táwọn sójà bá ń lọ sójú ogun, wọ́n máa ń da àṣíborí onírin borí lẹ́yìn tí wọ́n bá ti dé fìlà híhun tàbí aláwọ. Ọpẹ́lọpẹ́ àṣíborí yẹn, gbogbo ọta tí ì bá ti fọ́ agbárí sójà máa ń ta dànù ni tó bá ti bà á. Kí ni Pọ́ọ̀lù fẹ́ fà yọ nínú àpèjúwe yìí? Bí àṣíborí ṣe ń dàábò bo orí bẹ́ẹ̀ ni ìrètí ṣe ń dáàbò bo èrò inú, ìyẹn agbára ìrònú. Tó o bá ní ìrètí tó fẹsẹ̀ múlẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ète Ọlọ́run, ìbẹ̀rù ò ní lè gba àlàáfíà rẹ lọ́wọ́ rẹ bẹ́ẹ̀ lo ò sì ní sọ̀rètí nù nígbà tí ìṣòro bá dé. Ta ló wá lè sọ pé òun ò nílò irú àṣíborí bẹ́ẹ̀ nínú wa o?

      Pọ́ọ̀lù tún lo àpèjúwe kedere mìíràn láti fi bí ìrètí ṣe tan mọ́ ìfẹ́ Ọlọ́run hàn. Ó kọ̀wé pé: “Ìrètí yìí ni àwa ní gẹ́gẹ́ bí ìdákọ̀ró fún ọkàn, ó dájú, ó fìdí múlẹ̀ gbọn-in.” (Hébérù 6:19) Pọ́ọ̀lù mọ bí ìdákọ̀ró ṣe ṣe pàtàkì tó nítorí ó ju ẹ̀ẹ̀kan lọ tí ọkọ̀ ojú omi tó wọ̀ rì. Tí ìjì bá ṣọwọ́ òdì sí ọkọ̀ ojú omi, ńṣe làwọn atukọ̀ máa ń sọ ìdákọ̀ró sísàlẹ̀ odò. Bó bá jàjà rí nǹkan kọ́ nísàlẹ̀ odò, ó ṣeé ṣe kí ọkọ yẹn má dà nù, ó lè gúnlẹ̀ láyọ̀ dípò tí ì bá fi forí sọ àpáta ní bèbè odò.

      Bẹ́ẹ̀ gẹ́lẹ́, bí àwọn ìlérí Ọlọ́run bá dà bí ‘ìrètí tó dájú, tó fìdí múlẹ̀ gbọn-in’ fún wa, ìrètí yẹn á lè ràn wá lọ́wọ́ láti jàjàyè nínú ìjì tó ń jà láyé eléwu yìí. Jèhófà ṣèlérí pé láìpẹ́, àkókò ń bọ̀ tọmọ aráyé ò ní fojú winá ogun, ìwà ọ̀daràn, ìbànújẹ́ àti ikú pàápàá mọ́. (Wo àpótí tó wà lójú ìwé 20.) Tá a bá dìrọ̀ mọ́ ìrètí yìí, kò ní jẹ́ ká ṣe kòńgẹ́ ibi, á sì sún wa láti máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà Ọlọ́run dípò tá ó fi máa báwọn hùwà pálapàla táráyé ń hù lóde òní tó sì ń dojú ayé rú.

      Ìrètí tí Jèhófà ń nawọ́ rẹ̀ sí wa yìí kàn ọ́ gbọ̀ngbọ̀n. Ọlọ́run fẹ́ kó o gbé ìgbésí ayé rẹ gẹ́gẹ́ bó ṣe pète pé kó o gbé e. Ìfẹ́ ọkàn rẹ̀ ni pé “kí a gba gbogbo onírúurú ènìyàn là.” Báwo la ṣe máa gbà wọ́n là? Lákọ̀ọ́kọ́ ná, olúkúlùkù wọn gbọ́dọ̀ “wá sí ìmọ̀ pípéye nípa òtítọ́.” (1 Tímótì 2:4) Àwọn tó ń tẹ ìwé ìròyìn yìí gbà ọ́ níyànjú láti gba ìmọ̀ tó ń fúnni ní ìyè nípa òtítọ́ Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run sínú. Ìrètí tí Ọlọ́run yóò tipa bẹ́ẹ̀ fún ọ á ju ìrètí èyíkéyìí tó o lè rí nínú ayé yìí.

      Tó o bá ní irú ìrètí bẹ́ẹ̀, kò yẹ kó o máa wo ara ẹ bí aláìnírètí, nítorí pé Ọlọ́run lè fún ọ lókun tó o nílò kọ́wọ́ rẹ lè tẹ ohunkóhun tó o bá ń lépa, tó wà níbàámu pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ̀. (2 Kọ́ríńtì 4:7; Fílípì 4:13) Ṣe irú ìrètí tó o nílò kọ́ lèyí? Nítorí náà, tó o bá nílò ìrètí, tó o sì ti ń wá a káàkiri, mọ́kàn. Ìrètí ló dé tán yìí. Ọwọ́ rẹ lè tẹ̀ ẹ́!

      [Àpótí/Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 20]

      Ìdí Tá A Fi Lè Ní Ìrètí

      Àwọn èrò Ìwé Mímọ́ wọ̀nyí lè ràn ọ́ lọ́wọ́ láti fún ìrètí rẹ lágbára:

      ◼ Ọlọ́run ṣèlérí ọjọ́ iwájú aláyọ̀.

      Ọ̀rọ̀ rẹ̀ sọ pé gbogbo àgbáyé yóò di Párádísè níbi tí gbogbo aráyé á ti máa gbé gẹ́gẹ́ bí ìdílé kan, tí wọ́n sì wà ní ìṣọ̀kan.—Sáàmù 37:11, 29; Aísáyà 25:8; Ìṣípayá 21:3, 4.

      ◼ Ọlọ́run ò lè purọ́.

      Ó kórìíra irọ́ pípa ní gbogbo ọ̀nà. Jèhófà mọ́ tónítóní láìlábààwọ́n tàbí ó mọ́ gaara, nítorí náà kò ṣeé ṣe fún un láti purọ́.—Òwe 6:16-19; Aísáyà 6:2, 3; Títù 1:2; Hébérù 6:18.

      ◼ Agbára Ọlọ́run ò láàlà.

      Jèhófà nìkan ni alágbára ńlá. Kò sí nǹkan kan láyé yìí tó lè dí i lọ́wọ́ àtimú ète rẹ̀ ṣẹ.—Ẹ́kísódù 15:11; Aísáyà 40:25, 26.

      ◼ Ọlọ́run fẹ́ kó o wà láàyè títí láé.

      —Jòhánù 3:16; 1 Tímótì 2:3, 4.

      ◼ Ọlọ́run lérò rere sí wa.

      Ó mọ̀ọ́mọ̀ máa ń mójú kúrò lára àwọn ẹ̀bi àti ìkùdíẹ̀–káàtó wa, ṣùgbọ́n ó máa ń wo àwọn ànímọ́ rere àti ìsapá wa. (Sáàmù 103:12-14; 130:3; Hébérù 6:10) Ó máa ń retí pé a ó máa ṣe nǹkan tó dára, tá a bá sì ṣe bẹ́ẹ̀ inú rẹ̀ máa ń dùn.—Òwe 27:11.

      ◼ Ọlọ́run ṣèlérí pé òun á ràn wá lọ́wọ́ kí ọwọ́ wa bàa lè tẹ ohun tá à ń lépa, tó bá ìfẹ́ rẹ̀ mu.

      Kò yẹ káwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ máa wo ara wọn bí ẹni tí kò nírètí. Ọlọ́run máa ń fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ fàlàlà, ẹ̀mí Ọlọ́run yìí sì ni ipá tó lágbára jù tó lè ràn wá lọ́wọ́.—Fílípì 4:13.

      ◼ Ìrètí nínú Ọlọ́run kì í ṣákìí.

      Atóófaratì bí òkè ni Ọlọ́run, ó sì ṣeé gbẹ́kẹ̀ lé, kò ní padà lẹ́yìn rẹ láé.—Sáàmù 25:3.

      [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 22]

      Bí àṣíborí ṣe ń dáàbò bo orí bẹ́ẹ̀ ni ìrètí ṣe ń dáàbò bo èrò inú

      [Àwòrán tó wà ní ojú ìwé 22]

      Bí ìdákọ̀ró, ìrètí tó fẹsẹ̀ múlẹ̀ ṣinṣin lè fọkàn ẹni balẹ̀

      [Credit Line]

      Nípasẹ̀ ìyọ̀ǹda René Seindal/Su concessione del Museo Archeologico Regionale A. Salinas di Palermo

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́