-
Ṣé Ayé àti Ọ̀run Ní Ìbẹ̀rẹ̀?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
3. Kí ló mú káwa èèyàn yàtọ̀ sáwọn ẹranko?
Lẹ́yìn tí Jèhófà dá ayé, ó dá àwọn ohun abẹ̀mí sínú ẹ̀. Àwọn ewéko àtàwọn ẹranko ló kọ́kọ́ dá. Lẹ́yìn náà, “Ọlọ́run sì dá èèyàn ní àwòrán rẹ̀.” (Ka Jẹ́nẹ́sísì 1:27.) Kí ló mú káwa èèyàn ṣàrà ọ̀tọ̀ nínú gbogbo nǹkan tí Ọlọ́run dá? Ohun tó mú ká ṣàrà ọ̀tọ̀ ni pé àwòrán Ọlọ́run ni wá, torí náà a lè ní àwọn ìwà àti ìṣe tí Ọlọ́run ní, irú bí ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo. Ó tún dá wa lọ́nà tá a fi lè kọ́ àwọn èdè tuntun, a lè mọyì àwọn ohun tó rẹwà, a sì lè gbádùn orin lóríṣiríṣi. Ohun míì tá a tún lè ṣe àmọ́ táwọn ẹranko ò lè ṣe ni pé a lè jọ́sìn Ẹlẹ́dàá wa.
-
-
Ṣé Ayé àti Ọ̀run Ní Ìbẹ̀rẹ̀?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
6. Ọ̀nà tó ṣàrà ọ̀tọ̀ ni Ọlọ́run gbà dá àwa èèyàn
Àwa èèyàn yàtọ̀ pátápátá sáwọn ẹranko tí Jèhófà dá. Ka Jẹ́nẹ́sísì 1:26, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Torí pé Ọlọ́run dá wa ní àwòrán ara ẹ̀, àwa èèyàn máa ń fi ìfẹ́ àti àánú hàn, kí nìyẹn ń sọ fún wa nípa irú ẹni tí Ọlọ́run jẹ́?
-