-
Àkọsílẹ̀ Nípa Ọjọ́ Nóà—Ǹjẹ́ ó Ṣe Pàtàkì Fún wa?Ilé Ìṣọ́—2003 | May 15
-
-
Ní báyìí, jọ̀wọ́ ka Jẹ́nẹ́sísì 8:5-17. Ó fẹ́rẹ̀ẹ́ tó oṣù méjì àtààbọ̀ (ọjọ́ mẹ́tàléláàádọ́rin) lẹ́yìn náà kí ṣóńṣó orí àwọn òkè tó fara hàn, “ní oṣù kẹwàá [June], ní ọjọ́ kìíní oṣù.” (Jẹ́nẹ́sísì 8:5)b Oṣù mẹ́ta (àádọ́rùn-ún ọjọ́) lẹ́yìn náà—ìyẹn ní “ọdún kọkàn-lé-lẹ́gbẹ̀ta [tí Nóà ti wà láyé], ní oṣù kìíní, ní ọjọ́ kìíní oṣù,” tàbí ní ìdajì oṣù September, ọdún 2369 ṣááju Sànmánì Tiwa—Nóà ṣí ìbòrí áàkì náà kúrò. Ìgbà yẹn ló wá rí i pé “orí ilẹ̀ ti gbẹ.” (Jẹ́nẹ́sísì 8:13) Ní oṣù kan àti ọjọ́ mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n (ọjọ́ mẹ́tàdínlọ́gọ́ta) lẹ́yìn èyí, “ní oṣù kejì, ní ọjọ́ kẹtàdínlọ́gbọ̀n oṣù [ní ìdajì oṣù November, ọdún 2369 ṣááju Sànmánì Tiwa], ilẹ̀ ayé sì ti gbẹ tán.” Nóà àti ìdílé rẹ̀ wá jáde kúrò nínú ọkọ̀ áàkì náà sórí ilẹ̀ tó ti gbẹ táútáú. Nítorí náà, odindi ọdún kan gbáko àti ọjọ́ mẹ́wàá (ọgbọ̀n dín nírínwó ọjọ́) ni Nóà àtàwọn tó kù lò nínú ọkọ̀ áàkì náà.—Jẹ́nẹ́sísì 8:14.
-
-
Àkọsílẹ̀ Nípa Ọjọ́ Nóà—Ǹjẹ́ ó Ṣe Pàtàkì Fún wa?Ilé Ìṣọ́—2003 | May 15
-
-
b Ìwé Keil-Delitzsch Commentary on the Old Testament, Apá Kìíní, ojú ìwé 148, sọ pé: “Ó ṣeé ṣe kó jẹ́ pé ọjọ́ kẹtàléláàádọ́rin [73] lẹ́yìn tí ọkọ̀ áàkì náà gúnlẹ̀ ni ṣóńṣó orí àwọn òkè tó fara hàn, ìyẹn ṣóńṣó orí àwọn òkè Armenia tó yí ọkọ̀ áàkì náà ká lọ́tùn-ún lósì.”
-