-
Ní Irú Ìgbàgbọ́ Tí Ábúráhámù Ní!Ilé Ìṣọ́—2001 | August 15
-
-
10. Ìṣòro wo ló dìde láàárín àwọn darandaran Ábúrámù àti ti Lọ́ọ̀tì, èé sì ti ṣe tó fi pọndandan pé kí wọ́n tètè yanjú rẹ̀?
10 “Wàyí o, Lọ́ọ̀tì pẹ̀lú, ẹni tí ń bá Ábúrámù lọ, ní àwọn àgùntàn àti màlúù àti àwọn àgọ́. Nítorí èyí, ilẹ̀ náà kò gba gbogbo wọn láti máa gbé pa pọ̀, nítorí pé ẹrù wọn ti di púpọ̀, gbogbo wọn kò sì lè máa gbé pa pọ̀. Aáwọ̀ sì dìde láàárín àwọn olùda ohun ọ̀sìn Ábúrámù àti àwọn olùda ohun ọ̀sìn Lọ́ọ̀tì; ní àkókò yẹn, àwọn ọmọ Kénáánì àti àwọn Pérísì sì ń gbé ní ilẹ̀ náà.” (Jẹ́nẹ́sísì 13:5-7) Omi àti pápá ìjẹko tó wà ní ilẹ̀ náà kò tó àwọn agbo ẹran Ábúrámù àti ti Lọ́ọ̀tì mọ́. Ni èdèkòyédè àti gbúngbùngbún bá bẹ́ sílẹ̀ láàárín àwọn darandaran náà. Irú aáwọ̀ bẹ́ẹ̀ ò sì yẹ àwọn olùjọsìn Ọlọ́run tòótọ́. Bí wọn ò bá sì tètè yanjú awuyewuye yìí, ó lè dá ìjà tí kò ní tán sílẹ̀. Báwo wá ni Ábúrámù ṣe máa yanjú ọ̀ràn tó délẹ̀ yìí? Ó ti gba Lọ́ọ̀tì ṣọmọ lẹ́yìn tí bàbá Lọ́ọ̀tì kú, ó sì ṣeé ṣe kó jẹ́ pé òun ló tọ́ ọ dàgbà bíi pé ọmọ tirẹ̀ gan-an ni. Nígbà tó sì jẹ́ pé Ábúrámù làgbà, ṣé kò lẹ́tọ̀ọ́ láti yan ibi tó dára jù lọ fún ara rẹ̀ ni?
11, 12. Àǹfààní ńlá wo ni Ábúrámù nawọ́ rẹ̀ sí Lọ́ọ̀tì, èé sì ti ṣe tí ibi tí Lọ́ọ̀tì yàn kò fi bọ́gbọ́n mu?
11 Ṣùgbọ́n “Ábúrámù sọ fún Lọ́ọ̀tì pé: ‘Jọ̀wọ́, má ṣe jẹ́ kí aáwọ̀ máa bá a lọ láàárín èmi àti ìwọ àti láàárín àwọn olùṣọ́ agbo ẹran mi àti àwọn olùṣọ́ agbo ẹran rẹ, nítorí arákùnrin ni wá. Gbogbo ilẹ̀ kò ha wà lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ? Jọ̀wọ́, yà sọ́tọ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi. Bí ìwọ bá lọ sí apá òsì, nígbà náà, èmi yóò lọ sí apá ọ̀tún; ṣùgbọ́n bí ìwọ bá lọ sí apá ọ̀tún, nígbà náà, èmi yóò lọ sí apá òsì.’” Ibì kan ń bẹ nítòsí Bẹ́tẹ́lì tí wọ́n sọ pé ó jẹ́ “ọ̀kan lára ibi tó dára jù lọ láti dúró sí wo òréré Palẹ́sìnì.” Bóyá látibẹ̀, “Lọ́ọ̀tì gbé ojú rẹ̀ sókè, ó sì rí gbogbo Àgbègbè Jọ́dánì, pé gbogbo rẹ̀ jẹ́ ẹkùn ilẹ̀ olómi púpọ̀ kí Jèhófà tó run Sódómù àti Gòmórà, bí ọgbà Jèhófà, bí ilẹ̀ Íjíbítì títí dé Sóárì.”—Jẹ́nẹ́sísì 13:8-10.
-
-
Ní Irú Ìgbàgbọ́ Tí Ábúráhámù Ní!Ilé Ìṣọ́—2001 | August 15
-
-
13. Báwo ni àpẹẹrẹ Ábúrámù ṣe lè ṣèrànwọ́ fáwọn Kristẹni tó bá ń ṣawuyewuye lórí ọ̀ràn owó?
13 Ábúrámù ní tirẹ̀ gba ìlérí Jèhófà gbọ́, pé irú ọmọ òun ni yóò jogún gbogbo ilẹ̀ yẹn bópẹ́ bóyá; kò tiẹ̀ ṣòpò ṣawuyewuye nítorí apá kékeré kan lára ilẹ̀ náà. Ó fi ọ̀ràn náà ṣe osùn, ó fi pa ara, ó gbégbèésẹ̀ níbàámu pẹ̀lú ìlànà táa gbé kalẹ̀ lẹ́yìn náà nínú 1 Kọ́ríńtì 10:24, pé: “Kí olúkúlùkù má ṣe máa wá àǹfààní ti ara rẹ̀, bí kò ṣe ti ẹnì kejì.” Ìránnilétí tó dára rèé fáwọn ará tó bá ń bára wọn fa wàhálà nítorí ọ̀ràn owó. Dípò kí àwọn kan tẹ̀ lé ìmọ̀ràn tó wà nínú Mátíù 18:15-17, ńṣe ni wọ́n ń gbé arákùnrin wọn lọ sílé ẹjọ́. (1 Kọ́ríńtì 6:1, 7) Àpẹẹrẹ Ábúrámù fi hàn pé ó sàn kéèyàn pàdánù owó ju pé kó mú ẹ̀gàn bá orúkọ Jèhófà tàbí kí ó ṣe nǹkan tó máa da ìjọ Kristẹni rú.—Jákọ́bù 3:18.
-