-
Agbára ÀdúràIlé Ìṣọ́—2000 | March 1
-
-
ÉLÍÉSÉRÌ nígbàgbọ́ nínú agbára àdúrà. Pẹ̀lú ìgbàgbọ́ tó jọni lójú, táa lè fi wé ti ọmọdé, ó fi tìrẹ̀lẹ̀-tìrẹ̀lẹ̀ gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ yìí, ó ní: “Jèhófà Ọlọ́run ọ̀gá mi Ábúráhámù, jọ̀wọ́, mú kí ó ṣẹlẹ̀ níwájú mi ní òní yìí, kí o sì ṣe inú-rere-onífẹ̀ẹ́ sí ọ̀gá mi Ábúráhámù. Kíyè sí i, èmi dúró níbi ìsun omi, àwọn ọmọbìnrin àwọn ọkùnrin ìlú ńlá náà sì ń jáde bọ̀ wá fa omi. Kí ó ṣẹlẹ̀ pé ọ̀dọ́bìnrin tí èmi bá wí fún pé, ‘Jọ̀wọ́, sọ ìṣà omi rẹ kalẹ̀, kí èmi lè mu,’ tí yóò sì wí ní ti gidi pé, ‘Mu, èmi yóò sì tún fi omi fún àwọn ràkúnmí rẹ,’ ẹni yìí ni kí o yàn fún ìránṣẹ́ rẹ, fún Ísákì; kí o sì tipa èyí jẹ́ kí n mọ̀ pé o ti fi ìfẹ́ dídúró ṣinṣin hàn sí ọ̀gá mi.”—Jẹ́nẹ́sísì 24:12-14.
-
-
Agbára ÀdúràIlé Ìṣọ́—2000 | March 1
-
-
Ẹ̀kọ́ táa lè rí kọ́ nínú àdúrà Élíésérì pọ̀ jọjọ. Ó fi hàn pé ó nígbàgbọ́ tó ta yọ, ó lẹ́mìí ìrẹ̀lẹ̀, àìmọtara-ẹni-nìkan tó sì ní lórí ọ̀ràn àwọn ẹlòmíràn tún pabanbarì. Àdúrà Élíésérì tún fi hàn pé ó jẹ́ ẹni tó ń fara mọ́ ọ̀nà tí Jèhófà gbà ń bá aráyé lò. Kò sí àní-àní pé ó mọ̀ pé ọ̀rẹ́ Ọlọ́run ni Ábúráhámù, ó sì tún mọ̀ nípa ìlérí Rẹ̀ pé ìbùkún ọjọ́ ọ̀la yóò dé sórí aráyé nípasẹ̀ Ábúráhámù. (Jẹ́nẹ́sísì 12:3) Nípa báyìí, Élíésérì bẹ̀rẹ̀ àdúrà rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ yìí: “Jèhófà Ọlọ́run ọ̀gá mi Ábúráhámù.”
-