-
Ohun Kan Tó Níye Lórí Ju Àwọn Ìṣúra Íjíbítì LọIlé Ìṣọ́—2002 | June 15
-
-
Kò pẹ́ tí Míríámù fi sá dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, tó sì sọ pé: ‘Ṣé kí n lọ bá ọ wá obìnrin Hébérù kan wá kí ó lè máa bá ọ tọ́jú ọmọ náà?’ Àwọn kan sọ pé kàyéfì gbáà ni ìtàn yìí jẹ́. Ẹ̀gbọ́n Mósè yàtọ̀ pátápátá sí Fáráò tí òun àtàwọn ẹmẹ̀wà rẹ̀ jùmọ̀ “ta ọgbọ́n” láti ba ti àwọn Hébérù jẹ́. Àmọ́ o, ìgbà tí ọmọbìnrin ọba náà fara mọ́ ohun tí ẹ̀gbọ́n Mósè wí ni ìdánilójú tó wà pé Mósè ti bọ́ lọ́wọ́ ikú. Ọmọbìnrin Fáráò dáhùn pé: “Lọ!” Ojú ẹsẹ̀ ni Míríámù lọ pe ìyá rẹ̀ wá. Lẹ́yìn tí wọ́n dúnàádúrà, ó wá háyà Jókébédì láti tọ́jú ọmọ ara rẹ̀ lábẹ́ ààbò ọba.—Ẹ́kísódù 2:5-9.
-
-
Ohun Kan Tó Níye Lórí Ju Àwọn Ìṣúra Íjíbítì LọIlé Ìṣọ́—2002 | June 15
-
-
[Àpótí tó wà ní ojú ìwé 11]
Iṣẹ́ Abánitọ́mọ
Àwọn ìyá ló máa ń fún àwọn ọmọ wọn lọ́yàn mu. Àmọ́, ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ nì, Brevard Childs, sọ nínú ìwé Journal of Biblical Literature pé, “nígbà mìíràn, àwọn ìdílé ọ̀tọ̀kùlú [ìhà Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn] máa ń háyà abánitọ́mọ. Àṣà yìí tún wọ́pọ̀ níbi tí ìyá náà ò bá ti lè tọ́jú ọmọ rẹ̀ tàbí níbi tí wọn ò bá ti mọ ìyá tó bí ọmọ náà. Ẹrù iṣẹ́ abánitọ́mọ náà ni pé kó tọ́jú ọmọ náà, kó sì máa fún un lọ́yàn mu láàárín àkókò tí wọ́n jọ fọwọ́ sí náà.” Àwọn ìwé kan tá a fi òrépèté ṣe láti ìhà Àárín Gbùngbùn Ìlà Oòrùn ṣì wà títí di báyìí, tó sọ̀rọ̀ nípa àdéhùn iṣẹ́ pẹ̀lú àwọn abánitọ́mọ. Àkọsílẹ̀ wọ̀nyí jẹ́rìí sí àṣà tó gbòde láti sáà àwọn ẹ̀yà Sumer títí di sáà àwọn Hélénì ní Íjíbítì. Àwọn apá tó wọ́pọ̀ jù nínú àwọn àkọsílẹ̀ wọ̀nyí ni ohun tí ẹnì kọ̀ọ̀kan tí ọ̀ràn kàn sọ, irú bí àkókò àdéhùn náà ti máa gùn tó, bí iṣẹ́ náà ṣe máa rí, ọ̀rọ̀ nípa oúnjẹ, owó ìtanràn tí ẹnì kan kò bá mú àdéhùn rẹ̀ ṣẹ, owó iṣẹ́, àti bí wọ́n á ṣe máa san owó náà. Ọ̀gbẹ́ni Childs ṣàlàyé pé, ohun tó sábà máa ń ṣẹlẹ̀ ni pé “iṣẹ́ ìtọ́jú yìí máa ń gbà tó ọdún méjì sí mẹ́ta. Inú ilé abánitọ́mọ ló ti máa tọ́jú ọmọ náà, àmọ́ yóò máa mú ọmọ ọ̀hún lọ sọ́dọ̀ ẹni tó ní in lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan fún àyẹ̀wò.”
-