ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Bá a Ṣe Lè Nífẹ̀ẹ́ Ọmọnìkejì Wa
    Ilé Ìṣọ́—2006 | December 1
    • Ta Ni Ọmọnìkejì Mi?

      4. Gẹ́gẹ́ bí Léfítíkù orí kọkàndínlógún ti sọ, àwọn wo làwọn Júù gbọ́dọ̀ máa fìfẹ́ hàn sí?

      4 Nígbà tí Jésù ń sọ fáwọn Farisí pé àṣẹ kejì tó tóbi jù lọ ni kéèyàn nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ̀ bí ara rẹ̀, òfin kan pàtó tí Ọlọ́run fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ló ń tọ́ka sí. Òfin yìí wà nínú Léfítíkù 19:18. Nínú orí kan náà yẹn, Ọlọ́run sọ fáwọn Júù pé kí wọ́n ka àwọn mìíràn tí kì í ṣe ọmọ Ísírẹ́lì sí ọmọnìkejì wọn. Ẹsẹ kẹrìnlélọ́gbọ̀n sọ pé: “Kí àtìpó tí ń ṣe àtìpó lọ́dọ̀ yín dà bí ọmọ ìbílẹ̀ yín; kí ìwọ sì nífẹ̀ẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ, nítorí ẹ di àtìpó ní ilẹ̀ Íjíbítì.” Nípa bẹ́ẹ̀, wọ́n gbọ́dọ̀ fìfẹ́ hàn sáwọn tí kì í ṣe Júù, àgàgà àwọn aláwọ̀ṣe, ìyẹn àwọn tó yí padà di ẹlẹ́sìn Júù.

  • Bá a Ṣe Lè Nífẹ̀ẹ́ Ọmọnìkejì Wa
    Ilé Ìṣọ́—2006 | December 1
    • Bá A Ṣe Lè Nífẹ̀ẹ́ Ọmọnìkejì Wa

      8. Kí ni Léfítíkù orí kọkàndínlógún sọ nípa bó ṣe yẹ ká máa fìfẹ́ hàn sáwọn èèyàn?

      8 Bí ìfẹ́ fún Ọlọ́run ṣe rí náà ni ìfẹ́ fún ọmọnìkejì ẹni ṣe rí, kì í ṣe ohun téèyàn kàn ń rò lọ́kàn, ó gba pé ká ṣe ohun kan. Á dára ká túbọ̀ gbé àwọn ọ̀rọ̀ tó yí òfin tó wà nínú Léfítíkù orí kọkàndínlógún yẹn yẹ̀ wò, èyí tó gba àwọn èèyàn Ọlọ́rùn níyànjú láti nífẹ̀ẹ́ aládùúgbò wọn bí ara wọn. Ibẹ̀ la ti kà á pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbọ́dọ̀ fún àwọn ẹni tí ìṣẹ́ ń ṣẹ́ àtàwọn àtìpó láyè láti nípìn-ín nínú irè oko wọn. Ìyẹn ni kò ní jẹ́ kí wọ́n jalè, kò ní jẹ́ kí wọ́n hùwà ẹ̀tàn, tàbí kí wọ́n máa ṣe màgòmágó. Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò gbọ́dọ̀ ṣojúsàájú tó bá kan ọ̀ràn ìdájọ́. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n lè báni wí nígbà tó bá yẹ kí wọ́n ṣe bẹ́ẹ̀, síbẹ̀ òfin Ọlọ́run sọ fún wọn ní pàtó pé: “Ìwọ kò gbọ́dọ̀ kórìíra arákùnrin rẹ nínú ọkàn-àyà rẹ.” Èyí àtàwọn àṣẹ mìíràn ni Jésù kó pọ̀ nígbà tó sọ pé: “Kí ìwọ sì nífẹ̀ẹ́ ọmọnìkejì rẹ gẹ́gẹ́ bí ara rẹ.”—Léfítíkù 19:9-11, 15, 17, 18.

      9. Kí nìdí tí Jèhófà fi pàṣẹ fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé kí wọ́n ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn?

      9 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbọ́dọ̀ fìfẹ́ hàn sáwọn ẹlòmíràn, síbẹ̀ wọ́n tún gbọ́dọ̀ ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn tó jẹ́ abọ̀rìṣà. Jèhófà kìlọ̀ fún wọn nípa ewu tó wà nínú kíkó ẹgbẹ́ búburú àti àbájáde tó máa ń ní. Bí àpẹẹrẹ, àṣẹ tí Jèhófà pa fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì nípa àwọn orílẹ̀-èdè táwọn ọmọ Ísírẹ́lì máa gba ilẹ̀ wọn ni pé: “Ìwọ kò sì gbọ́dọ̀ bá wọn dána. Ọmọbìnrin rẹ ni ìwọ kò gbọ́dọ̀ fi fún ọmọkùnrin rẹ̀, ọmọbìnrin rẹ̀ sì ni ìwọ kò gbọ́dọ̀ mú fún ọmọkùnrin rẹ. Nítorí òun yóò yí ọmọ rẹ padà láti má ṣe tọ̀ mí lẹ́yìn, dájúdájú, wọn yóò sì máa sin àwọn ọlọ́run mìíràn; ní tòótọ́, ìbínú Jèhófà yóò sì ru sí yín.”—Diutarónómì 7:3, 4.

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́