-
“Israeli Ọlọrun” àti “Ogunlọ́gọ̀ Ńlá”Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 1
-
-
8 Nígbà tí wọ́n bá jẹ́ olùṣòtítọ́, Israeli máa ń jẹ́wọ́ ipò ọba-aláṣẹ Jehofa wọ́n sì máa ń tẹ́wọ́gbà á gẹ́gẹ́ bí Ọba wọn. (Isaiah 33:22) Nípa báyìí, wọ́n jẹ́ ìjọba kan. Ṣùgbọ́n, gẹ́gẹ́ bí a ti ṣí i payá lẹ́yìn náà, ìlérí náà nípa “ìjọba kan” yóò túmọ̀ sí ju ìyẹn pàápàá lọ. Síwájú síi, nígbà tí wọ́n bá ṣègbọràn sí Òfin Jehofa, wọ́n máa ń mọ́ tónítóní, tí wọ́n sì máa ń ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká. Wọ́n jẹ́ orílẹ̀-èdè mímọ́. (Deuteronomi 7:5, 6) Wọ́n ha jẹ́ ìjọba àlùfáà bí? Tóò, ní Israeli ìran Lefi ni a yà sọ́tọ̀ fún iṣẹ́-ìsìn ní tẹmpili, láàárín ẹ̀yà náà sì ni ẹgbẹ́ àlùfáà Lefi wà. Nígbà tí a fìdí Òfin Mose lọ́lẹ̀, àwọn ọmọkùnrin Lefi ni a fi ṣe pàṣípààrọ̀ fún àwọn àkọ́bí gbogbo ìdílé tí kì í ṣe ti Lefi.a (Eksodu 22:29; Numeri 3:11-16, 40-51) Nípa báyìí, gẹ́gẹ́ bí a ti lè sọ pé ó jẹ́, gbogbo ìdílé ní Israeli ni a ṣojú fún nínú iṣẹ́-ìsìn ní tẹmpili. Èyí ni ipò tí ó fara jọ ipo àlùfáà jùlọ tí orílẹ̀-èdè náà ní. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n ṣojú fún Jehofa níwájú àwọn orílẹ̀-èdè. Àjèjì yòówù tí ó bá fẹ́ láti jọ́sìn Ọlọrun òtítọ́ náà níláti ṣe bẹ́ẹ̀ ní ìsopọ̀ pẹ̀lú Israeli.—2 Kronika 6:32, 33; Isaiah 60:10.
-
-
“Israeli Ọlọrun” àti “Ogunlọ́gọ̀ Ńlá”Ilé-Ìṣọ́nà—1995 | July 1
-
-
a Nígbà tí a fìdí ipò àlùfáà Israeli lọ́lẹ̀, àwọn ọmọkùnrin àkọ́bí tí kì í ṣe láti ìran Lefi ti Israeli àti àwọn ọmọkùnrin láti ìran Lefi ni a kà. Àkọ́bí 273 ni ó fi lé sí ti àwọn ọmọkùnrin Lefi. Nítorí ìdí èyí, Jehofa pàṣẹ pé kí a san ṣékélì márùn-ún lórí ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn 273 náà gẹ́gẹ́ bí ìràpadà fún èyí tí ó fi lé.
-