-
Ohun Tó Yẹ Ká Mọ̀ Nípa Àwọn Áńgẹ́lìGbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
5. Má ṣe da nǹkan pọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn
Ọ̀tá Jèhófà ni Sátánì àtàwọn ẹ̀mí èṣù. Wọ́n tún jẹ́ ọ̀tá tiwa náà. Ka Lúùkù 9:38-42, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Kí làwọn ẹ̀mí èṣù máa ń ṣe fáwọn èèyàn?
A ò gbọ́dọ̀ da nǹkan pọ̀ pẹ̀lú àwọn ẹ̀mí èṣù lọ́nàkọnà. Ka Diutarónómì 18:10-12, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè yìí:
Àwọn ọ̀nà wo ni àwọn ẹ̀mí èṣù máa ń gbà bá àwọn èèyàn sọ̀rọ̀, tí wọ́n sì ń ṣì wọ́n lọ́nà? Àwọn ọ̀nà wo làwọn èèyàn máa ń gbà lọ́wọ́ sí ẹ̀mí òkùnkùn ládùúgbò yín?
Ṣé o rò pé ó bọ́gbọ́n mu bí Jèhófà ṣe sọ pé ká má ṣe bá àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn da nǹkan pọ̀? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?
Wo FÍDÍÒ yìí, lẹ́yìn náà kó o dáhùn àwọn ìbéèrè tó tẹ̀ lé e.
Ṣé o rò pé ó léwu bí Palesa ṣe so ońdè mọ́ ọmọ ẹ̀ lọ́wọ́? Kí nìdí tó o fi sọ bẹ́ẹ̀?
Kí ló yẹ kí Palesa ṣe tí kò bá fẹ́ káwọn ẹ̀mí èṣù máa da òun láàmù?
Ọjọ́ pẹ́ táwọn Kristẹni ti ń máa ń gbéjà ko àwọn ẹ̀mí ẹ̀ṣù. Ka Iṣe 19:19 àti 1 Kọ́ríńtì 10:21, lẹ́yìn náà kó o dáhùn ìbéèrè yìí:
Tó o bá ní ohunkóhun lọ́wọ́ tó ní í ṣe pẹ̀lú ẹ̀mí òkùnkùn, kí nìdí tó fi yẹ kó o dáná sun ún?
-
-
Kí Ló Ń Ṣẹlẹ̀ Sáwọn Tó Ti Kú?Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
-
-
2. Àǹfààní wo ló máa ṣe wá tá a bá mọ ohun tí Bíbélì sọ pé ikú jẹ́?
Ọ̀pọ̀ èèyàn ń bẹ̀rù ikú, kódà wọ́n tún ń bẹ̀rù àwọn òkú! Àmọ́, ọkàn ẹ máa balẹ̀ tó o bá mọ ohun tí Bíbélì sọ nípa ikú. Jésù sọ pé: ‘Òtítọ́ á sọ yín di òmìnira.’ (Jòhánù 8:32) Àwọn ẹlẹ́sìn kan ń kọ́ni pé ohun kan máa ń kúrò nínú èèyàn lẹ́yìn tó bá kú, tí ohun náà á sì máa wà láàyè nìṣó, àmọ́ Bíbélì ò sọ bẹ́ẹ̀. Torí náà, èèyàn kì í jẹ̀rora lẹ́yìn tó bá ti kú. Yàtọ̀ síyẹn, torí pé àwọn tó ti kú ò mọ nǹkan kan, wọn ò lè ṣe wá níkà. Èyí fi hàn pé kò yẹ ká máa tu àwọn òkú lójú tàbí ká máa jọ́sìn wọn, bẹ́ẹ̀ sì ni kò yẹ ká máa gbàdúrà fún wọn.
Àwọn kan sọ pé àwọn lè bá òkú sọ̀rọ̀. Àmọ́ ìyẹn ò ṣeé ṣe. A ti kà á nínú Bíbélì lẹ́ẹ̀kan pé “àwọn òkú kò mọ nǹkan kan rárá.” Àwọn kan rò pé àwọn èèyàn wọn tó ti kú làwọn ń bá sọ̀rọ̀, àmọ́ wọn ò mọ̀ pé àwọn ẹ̀mí èṣù làwọn ń bá sọ̀rọ̀, torí àwọn ẹ̀mí èṣù máa ń ṣe bíi pé àwọn lẹni tó ti kú. Torí náà, tá a bá mọ ohun tí Bíbélì sọ pé ikú jẹ́, ó máa dáàbò bò wá lọ́wọ́ àwọn ẹ̀mí èṣù. Jèhófà kìlọ̀ fún wa pé a ò gbọ́dọ̀ bá àwọn òkú sọ̀rọ̀ torí ó mọ̀ pé tá a bá ń bá àwọn ẹ̀mí èṣù da nǹkan pọ̀, ó máa ṣe wá ní jàǹbá.—Ka Diutarónómì 18:10-12.
-