-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
18 Torí náà, àwọn méjèèjì ń bá ìrìn àjò wọn lọ sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù. Ọ̀nà náà jìn gan-an ni. Ìwádìí kan tiẹ̀ fi hàn pé ó lè gbà tó ọ̀sẹ̀ kan kí wọ́n tó débẹ̀. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn méjèèjì ló ń ṣọ̀fọ̀, ó dájú pé wọ́n á máa tu ara wọn nínú bí wọ́n ṣe jọ ń lọ.
-
-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
21 Lẹ́yìn-ọ̀-rẹyìn, Náómì àti Rúùtù dé Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, abúlé kan tó wà ní nǹkan bíi kìlómítà mẹ́wàá ní apá gúúsù Jerúsálẹ́mù. Ó jọ pé àwọn tó wà ní ìlú kékeré náà ti mọ ìdílé Náómì dáadáa tẹ́lẹ̀, torí kíá ni ìròyìn ti tàn kálẹ̀ pé Náómì ti pa dà dé. Bí àwọn obìnrin ìlú náà ṣe ń rí i ni wọ́n ń sọ pé, “Ṣé Náómì nìyí?” Ó dájú pé àkókò tí Náómì fi gbé ní ilẹ̀ Móábù ti mú kó yí pa dà gan-an. Ó hàn lójú rẹ̀ pé ó ti fara da ìnira àti ìbànújẹ́ fún ọ̀pọ̀ ọdún, ìrísí rẹ̀ sì tún yàtọ̀.—Rúùtù 1:19.
-