-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Ilé Ìṣọ́—2012 | July 1
-
-
Bí àwọn méjèèjì ṣe ń bá ìrìn àjò ọ̀nà jíjìn wọn lọ sí ìlú Bẹ́tílẹ́hẹ́mù nìyẹn. Ìwádìí kan fi hàn pé ìrìn àjò yẹn máa gbà tó ọ̀sẹ̀ kan. Àmọ́ ó dájú pé bí àwọn méjèèjì tó ń ṣọ̀fọ̀ ṣe jọ ń lọ, wọ́n á máa fi ìyẹn tu ara wọn nínú.
-
-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Ilé Ìṣọ́—2012 | July 1
-
-
Níkẹyìn, obìnrin méjèèjì yìí dé ìlú Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, abúlé kan tó wà ní nǹkan bíi kìlómítà mẹ́wàá níhà gúúsù Jerúsálẹ́mù. Ó jọ pé ìdílé Náómì jẹ́ ìdílé tó gbajúmọ̀ ní ìlú kékeré yìí, torí ṣe ni ìròyìn pé Náómì ti pa dà dé gba gbogbo ìlú náà. Àwọn obìnrin ìlú wá ń yọjú wò ó, wọ́n á ní, “Ṣé Náómì nìyí?” Ó hàn pé ilẹ̀ Móábù tí wọ́n lọ gbé ti mú kí ara rẹ̀ yí pa dà gan-an, torí ìrísí ojú rẹ̀ àti bó ṣe rí ní ìdúró fi hàn pé ọwọ́ ìyà àti ìpọ́njú ti bà á.—Rúùtù 1:19.
-