-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
23. Kí ni Rúùtù bẹ̀rẹ̀ sí í rò? Ètò wo ni Jèhófà ṣe fún àwọn aláìní nínú Òfin Mósè? (Tún wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
23 Bí àwọn méjèèjì ṣe bẹ̀rẹ̀ ìgbé ayé wọn tuntun ní ìlú Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, Rúùtù bẹ̀rẹ̀ sí í ronú nípa ọ̀nà tó dára jù lọ tí òun lè gbà máa gbọ́ bùkátà ara òun kí òun sì máa tọ́jú Náómì. Ó gbọ́ nípa ètò kan tí Jèhófà ṣe nínú Òfin tó fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí wọ́n jẹ́ èèyàn rẹ̀. Ètò yẹn fi hàn pé Jèhófà nífẹ̀ẹ́ àwọn tálákà. Ọlọ́run ní kí wọ́n fàyè gba àwọn tálákà láti lọ sí oko nígbà ìkórè. Kí wọ́n máa pèéṣẹ́ lẹ́yìn àwọn tó ń kórè, ìyẹn ni pé kí wọ́n máa ṣa àwọn irè oko tó bá ṣẹ́ kù sílẹ̀. Wọ́n sì tún lè máa kárúgbìn eteetí oko.b—Léf. 19:9, 10; Diu. 24:19-21.
24, 25. Kí ni Rúùtù ṣe nígbà tó ṣàdédé kan oko Bóásì? Kí lo lè sọ nípa iṣẹ́ pípèéṣẹ́?
24 Ní ìgbà ìkórè ọkà báálì, èyí tó máa bọ́ sí oṣù April lóde òní, Rúùtù jáde lọ sí pápá bóyá ó máa rí ẹni táá jẹ́ kó pèéṣẹ́ nínú oko rẹ̀. Ó ṣàdédé kan oko ọkùnrin kan tó ń jẹ́ Bóásì. Ọlọ́rọ̀ ni Bóásì, ó ní ilẹ̀ tó pọ̀, ó sì tún jẹ́ mọ̀lẹ́bí Élímélékì, ìyẹn ọkọ Náómì tó ti kú. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé òfin fàyè gba Rúùtù láti pèéṣẹ́, síbẹ̀ kò kàn wọnú oko olóko. Ó kọ́kọ́ tọrọ àyè lọ́wọ́ ọ̀dọ́kùnrin tó jẹ́ ọ̀gá àwọn olùkórè. Ọ̀dọ́kùnrin náà gbà fún un, Rúùtù sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ lójú ẹsẹ̀.—Rúùtù 1:22–2:3, 7.
-
-
“Ibi Tí O Bá Lọ Ni Èmi Yóò Lọ”Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
b Kò sí irú òfin bẹ́ẹ̀ ní ilẹ̀ Móábù tí Rúùtù ti wá, torí náà, ó máa jọ ọ́ lójú gan-an. Ní àwọn àgbègbè tó yí Ísírẹ́lì ká láyé ìgbà yẹn, ńṣe ni wọ́n máa ń fìyà jẹ àwọn opó. Ìwé ìwádìí kan sọ pé: “Tí ọkọ obìnrin kan bá ti kú, àwọn ọmọkùnrin tí opó náà bí lá máa tọ́jú rẹ̀. Tí kò bá ní ọmọkùnrin kankan, tí kò sì fẹ́ kú, ńṣe ló máa ta ara rẹ̀ sí oko ẹrú tàbí kó di aṣẹ́wó.”
-