-
“Ti Jèhófà Ni Ìjà Ogun Náà”Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016 | No. 5
-
-
Gòláyátì ni ọkùnrin náà! Dáfídì fojú ara rẹ̀ rí ohun tó fà á táwọn ọmọ ogun fi bẹ̀rù rẹ̀, ó ga gan-an, ó sì rí fìrìgbọ̀n. Kódà láìgbé aṣọ ogun wọ̀, ó wúwo ju àpapọ̀ ọkùnrin ńlá méjì lọ. Àmọ́ báyìí ó ti dira ogun, akínkanjú jagunjagun ni, ó sì lágbára. Gòláyátì pè wọ́n níjà pẹ̀lú ohùn rara. Fojú inú wo bó ṣe ń bú ramúramù táwọn ọmọ ogun á sì máa gbóhùn rẹ̀ bó ṣe ń pe Ísírẹ́lì àti Sọ́ọ̀lù ọba wọn níjà. Ó ní kí ẹni tó bá láyà jáde wá ko òun lójú!—1 Sámúẹ́lì 17:4-10.
-
-
“Ti Jèhófà Ni Ìjà Ogun Náà”Ilé Ìṣọ́ (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016 | No. 5
-
-
Dáfídì sọ̀rọ̀ akínkanjú níwájú ọba, ó ní: “Má ṣe jẹ́ kí ọkàn-àyà ọkùnrin èyíkéyìí rẹ̀wẹ̀sì nínú rẹ̀.” Ọkàn Sọ́ọ̀lù àtàwọn ọmọ ogun rẹ̀ ti pami nítorí Gòláyátì. Ó ṣeé ṣe kí wọ́n ti ṣe àṣìṣe tí ọ̀pọ̀ èèyàn máa ń ṣe, ìyẹn ni bí wọ́n ṣe wo ara wọn lẹ́gbẹ̀ẹ́ ọkùnrin fìrìgbọ̀n yìí, pé àwọn ò tiẹ̀ dé àyà rẹ̀. Wọ́n gbà pé ọwọ́ kan ló máa pa àwọn danù. Ṣùgbọ́n, Dáfídì ò ronú bẹ́ẹ̀ ní tiẹ̀. Bá a ṣe máa rí i níwájú, ojú tí Dáfídì fi wo ọ̀rọ̀ náà yàtọ̀ pátápátá sí tiwọn. Ló bá sọ pé òun máa lọ bá Gòláyátì jà.—1 Sámúẹ́lì 17:32.
-