-
Wọ́n Fara Da Ẹ̀gún Nínú Ẹran Ara WọnIlé Ìṣọ́—2002 | February 15
-
-
11. Kí ni Síbà sọ nípa Mẹfibóṣẹ́tì, ṣùgbọ́n báwo la ṣe mọ̀ pé irọ́ ló pa mọ́ ọn? (Wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
11 Nígbà tó tún yá, ẹ̀gún mìíràn tún bẹ̀rẹ̀ sí gún Mẹfibóṣẹ́tì lára. Síbà ìránṣẹ́ rẹ̀ purọ́ mọ́ ọn níwájú Dáfídì Ọba, tó ń sá fi Jerúsálẹ́mù sílẹ̀ nígbà yẹn, nítorí ọ̀tẹ̀ Ábúsálómù ọmọ rẹ̀. Síbà sọ pé Mẹfibóṣẹ́tì ti kẹ̀yìn sí Dáfídì. Ó ní ìyẹn ló jẹ́ kó jókòó pa sí Jerúsálẹ́mù, kí ó bàa lè gbàjọba.a Dáfídì gba irọ́ tí Síbà pa gbọ́. Ìyẹn ló jẹ́ kó pàṣẹ pé kí gbogbo dúkìá Mẹfibóṣẹ́tì di ti òpùrọ́ yẹn!—2 Sámúẹ́lì 16:1-4.
-
-
Wọ́n Fara Da Ẹ̀gún Nínú Ẹran Ara WọnIlé Ìṣọ́—2002 | February 15
-
-
a Onírẹ̀lẹ̀ èèyàn, tó moore ni Mẹfibóṣẹ́tì jẹ́. Kì í ṣe ẹ̀dá tó lè hu irú ìwà màkàrúrù bẹ́ẹ̀. Ó dájú pé ó mọ ìwà ìṣòtítọ́ tí Jónátánì, bàbá rẹ̀ hù. Bó tiẹ̀ jẹ́ pé ọmọ Sọ́ọ̀lù Ọba ni Jónátánì jẹ́, síbẹ̀ ó fi tìrẹ̀lẹ̀-tìrẹ̀lẹ̀ gbà pé Dáfídì ni Jèhófà yàn gẹ́gẹ́ bí ọba lórí Ísírẹ́lì. (1 Sámúẹ́lì 20:12-17) Gẹ́gẹ́ bí bàbá tó bẹ̀rù Ọlọ́run, Jónátánì bàbá Mẹfibóṣẹ́tì, tó tún jẹ́ ọ̀rẹ́ tó dúró ti Dáfídì gbágbáágbá, kò ní kọ́ ọmọ rẹ̀ pé kí ó dìtẹ̀ gbàjọba.
-