-
Èlíjà Gbé Ọlọ́run Tòótọ́ GaIlé Ìṣọ́—1998 | January 1
-
-
Nígbà tí Áhábù tajú kán rí Èlíjà, ó bi í pé: “Ṣé ìwọ rèé, ẹni tí ń mú ìtanùlẹ́gbẹ́ wá sórí Ísírẹ́lì?” Èlíjà fìgboyà fèsì pé: “Èmi kò mú ìtanùlẹ́gbẹ́ wá sórí Ísírẹ́lì, ṣùgbọ́n ìwọ àti ilé baba rẹ ni ó ṣe bẹ́ẹ̀, nítorí tí ẹ ti fi àwọn àṣẹ Jèhófà sílẹ̀, ẹ sì bẹ̀rẹ̀ sí tọ àwọn Báálì lẹ́yìn.” Lẹ́yìn náà Èlíjà pàṣẹ pé kí a kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ sí Òkè Kámẹ́lì, títí kan “àádọ́ta-lé-nírinwó wòlíì Báálì àti irínwó wòlíì òpó ọlọ́wọ̀.” Lẹ́yìn náà, Èlíjà bá àwùjọ náà sọ̀rọ̀ pé: “Yóò ti pẹ́ tó tí ẹ ó fi máa tiro lórí èrò méjì tí ó yàtọ̀ síra?a Bí Jèhófà bá ni Ọlọ́run tòótọ́, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn; ṣùgbọ́n bí Báálì bá ni, ẹ máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”—Àwọn Ọba Kìíní 18:17-21, NW.
-
-
Èlíjà Gbé Ọlọ́run Tòótọ́ GaIlé Ìṣọ́—1998 | January 1
-
-
a Àwọn ọ̀mọ̀wé akẹ́kọ̀ọ́jinlẹ̀ kan sọ pé Èlíjà lè máa sọ nípa ijó tí àwọn olùjọ́sìn Báálì máa ń jó nígbà ààtò ìsìn wọn. A lè rí ọ̀nà kan náà tí a gbà lo ọ̀rọ̀ náà, “tiro,” nínú Àwọn Ọba Kìíní 18:26 (NW) láti ṣàpèjúwe ijó àwọn wòlíì Báálì.
-