-
Ǹjẹ́ Kí Jèhófà Lè Sọ Pé O KáreIlé-Ìṣọ́nà—1996 | September 15
-
-
“Rántí mi Ọlọ́run mi, . . . Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere.”—NEHEMÁYÀ 13:22, 31.
-
-
Ǹjẹ́ Kí Jèhófà Lè Sọ Pé O KáreIlé-Ìṣọ́nà—1996 | September 15
-
-
2. (a) Ní àwọn ọ̀nà wo ni Nehemáyà gbà jíhìn tí ó dára nípa ara rẹ̀ fún Ọlọ́run? (b) Ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ wo ni Nehemáyà fi parí ìwé Bíbélì tí ń jẹ́ orúkọ rẹ̀?
2 Ọkùnrin kan tí ó jíhìn tí ó dára nípa ara rẹ̀ fún Ọlọ́run ni Nehemáyà, agbọ́tí Atasásítà (Longimanus), Ọba Páṣíà. (Nehemáyà 2:1) Nehemáyà di gómìnà àwọn Júù, ó sì tún odi Jerúsálẹ́mù kọ́ lójú àwọn ọ̀tá àti ewu. Pẹ̀lú ìtara fún ìjọsìn tòótọ́, ó mú Òfin Ọlọ́run ṣẹ, ó sì dàníyàn nípa àwọn tí a ni lára. (Nehemáyà 5:14-19) Nehemáyà rọ àwọn Léfì láti sọ ara wọn di mímọ́ nígbà gbogbo, kí wọ́n máa ṣọ́ ẹnubodè, kí wọn sì ya ọjọ́ Sábáàtì sí mímọ́. Nígbà náà, ó lè gbàdúrà pé: “Rántí mi Ọlọ́run mi nítorí èyí pẹ̀lú kí o sì dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ àánú rẹ.” Pẹ̀lúpẹ̀lù, lọ́nà tí ó bá a mu wẹ́kú, Nehemáyà mú ìwé onímìísí àtọ̀runwá rẹ̀ wá sí ìparí pẹ̀lú ìrawọ́ ẹ̀bẹ̀ náà pé: “Rántí mi, Ọlọ́run mi, fún rere.”—Nehemáyà 13:22, 31.
-