-
Ó Gbèjà Àwọn Èèyàn Ọlọ́runTẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
22. Kí nìdí tí ẹ̀rù fi ba Ẹ́sítérì láti lọ bá ọba tó jẹ́ ọkọ rẹ̀ sọ̀rọ̀? (Tún wo àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé.)
22 Àyà Ẹ́sítérì ti ní láti já nígbà tó gbọ́ nǹkan tí Módékáì ní kó ṣe. Àdánwò ńlá lèyí jẹ́ fún ìgbàgbọ́ Ẹ́sítérì. Bó ṣe dá Módékáì lóhùn láìfọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ fi hàn pé ẹ̀rù bà á. Ó rán Módékáì létí òfin ọba pé téèyàn bá tọ ọba Páṣíà lọ láìjẹ́ pé ọba ké sí i, ńṣe ni wọ́n máa pa á. Àyàfi bí ọba bá na ọ̀pá aládé wúrà rẹ̀ sí ẹni náà ni ikú fi máa yẹ̀ lórí rẹ̀. Ṣé ó wá yẹ kí Ẹ́sítérì ronú pé ọba máa fi àánú hàn sí òun lọ́nà yẹn, àgàgà tó bá rántí ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Fáṣítì nígbà tó kọ̀ láti jẹ́ ìpè ọba nígbà tí ọba pàṣẹ pé kó wá? Ẹ́sítérì sọ fún Módékáì pé ọba kò tíì pe òun láti ọgbọ̀n ọjọ́ sẹ́yìn! Níwọ̀n bó ti pẹ́ díẹ̀ tí ọba ti pa Ẹ́sítérì tì, ìdí púpọ̀ wà fún un láti máa ṣiyè méjì pé bóyá ọba tí èrò rẹ̀ lè yí pa dà nígbàkigbà yìí kò gba tòun mọ́.e—Ẹ́sít. 4:9-11.
-
-
Ó Gbèjà Àwọn Èèyàn Ọlọ́runTẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
-
-
e Sásítà Kìíní jẹ́ onínúfùfù, ìgbàkigbà ni èrò rẹ̀ sì lè yí pa dà. A rí àpẹẹrẹ èyí nínú ìtàn tí òpìtàn ọmọ ilẹ̀ Gíríìsì tó ń jẹ́ Herodotus kọ nípa ogun tí Sásítà bá ilẹ̀ Gíríìsì jà. Sásítà pàṣẹ pé kí wọ́n to ọkọ ojú omi sí ẹgbẹ́ ara wọn láti fi ṣe afárá sórí odò Hellespont. Nígbà tí ìjì ba afárá náà jẹ́, Sásítà pàṣẹ pé kí wọ́n bẹ́ orí àwọn ẹnjiníà tó ṣe afárá náà. Ó tiẹ̀ tún ní kí àwọn ìránṣẹ́ òun máa kó ẹgba bo odò Hellespont kí wọ́n sì máa ṣépè lé e lórí bíi ká sọ pé wọ́n ń fìyà jẹ omi odò náà. Lákòókò yìí kan náà, ọkùnrin ọlọ́rọ̀ kan wá bẹ Sásítà pé kó máà jẹ́ kí wọ́n mú ọmọ òun wọṣẹ́ ológun. Àmọ́, ńṣe ni Sásítà ní kí wọ́n gé ọmọ náà sí méjì, kí wọ́n sì gbé òkú rẹ̀ sí gbangba kó lè jẹ́ ìkìlọ̀ fún àwọn míì.
-