-
Fiyè Sí Àwọn Iṣẹ́ Àgbàyanu Ọlọ́runIlé Ìṣọ́—2001 | April 15
-
-
3. Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà nínú Jóòbù 38:22, 23, 25-29, kí ni àwọn nǹkan tí Ọlọ́run béèrè ìbéèrè nípa wọn?
3 Nígbà tí ọ̀rọ̀ débì kan, Ọlọ́run bi Jóòbù pé: “Ìwọ ha ti wọ àwọn ilé ìtọ́jú nǹkan pa mọ́ ti ìrì dídì, tàbí ìwọ ha rí àní àwọn ilé ìtọ́jú nǹkan pa mọ́ ti yìnyín, èyí tí mo pa mọ́ de àkókò wàhálà, de ọjọ́ ìjà àti ogun?” Ìrì dídì àti yìnyín kì í ṣàì wáyé láwọn ibi púpọ̀ láyé. Ọlọ́run ń bá ọ̀rọ̀ rẹ̀ lọ pé: “Ta ní la ipa ojú ọ̀nà fún ìkún omi àti ọ̀nà fún àwọsánmà ìjì tí ń sán ààrá, láti mú kí ó rọ̀ sórí ilẹ̀ níbi tí ènìyàn kankan kò sí, sórí aginjù nínú èyí tí ará ayé kankan kò sí, láti tẹ́ àwọn ibi tí ìjì kọlù àti ibi ahoro lọ́rùn, kí ó sì mú kí èéhù koríko hù? Òjò ha ní baba, tàbí, ta ní bí ìrì tí ń sẹ̀? Ikùn ta ni omi dídì ti jáde wá ní ti gidi, ní ti ìrì dídì wínníwínní ojú ọ̀run, ta sì ni ó bí i ní tòótọ́?”—Jóòbù 38:22, 23, 25-29.
-
-
Fiyè Sí Àwọn Iṣẹ́ Àgbàyanu Ọlọ́runIlé Ìṣọ́—2001 | April 15
-
-
7. Báwo ni òye ọmọ aráyé nípa òjò ti pọ̀ tó?
7 Òjò wá ńkọ́ o? Ọlọ́run bi Jóòbù pé: “Òjò ha ní baba, tàbí, ta ní bí ìrì tí ń sẹ̀?” Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ kan náà tó dá lórí ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì sọ pé: “Bó ṣe jẹ́ pé ọ̀nà tó díjú ni afẹ́fẹ́ gbà ń fẹ́ yí ká, tó sì jẹ́ pé onírúurú làwọn ohun tó para pọ̀ sínú afẹ́fẹ́, ó jọ pé kò ṣeé ṣe láti gbé àbá tó máa ṣe àlàyé kínníkínní kalẹ̀ pé báyìí ni ìkuukùu àti òjò ṣe ń pilẹ̀.” Ká sọ ọ́ lọ́nà tó máa yé tàgbàtèwe, àwọn onímọ̀ sáyẹ́ǹsì ti gbé oríṣiríṣi àbá kalẹ̀, àmọ́ wọn ò lè ṣe kúlẹ̀kúlẹ̀ àlàyé nípa òjò. Síbẹ̀, o sáà mọ̀ pé òjò tí ń gbé ìwàláàyè ró ń rọ̀, ó ń bomi rin ilẹ̀ ayé, ó ń mú kí ewéko dàgbà, ó ń jẹ́ kí ohun alààyè wà, kí ayé sì tù wọ́n lára.
-