ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • Ìdílé Jèhófà Ń Gbádùn Ìṣọ̀kan Ṣíṣeyebíye
    Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | July 15
    • 4. Ní ọ̀rọ̀ tìrẹ, báwo ni ìwọ yóò ṣe sọ ohun tí Orin Dáfídì 133 sọ nípa ìṣọ̀kan ará?

      4 Onísáàmù náà, Dáfídì, ní ìmọrírì jíjinlẹ̀ fún ìṣọ̀kan ará. A tilẹ̀ mí sí i láti kọrin nípa rẹ̀! Fojú inú wò ó, ti òun ti háápù rẹ̀, bí ó ti ń kọrin pé: “Kíyè sí i, ó ti dára ó sì ti dùn tó fún àwọn ará láti máa jùmọ̀ gbé ní ìrẹ́pọ̀. Ó dà bí òróró ìkunra iyebíye ní orí, tí ó ṣàn dé irùngbọ̀n, àní irùngbọ̀n Áárónì: tí ó sì ṣàn sí etí aṣọ rẹ̀; bí ìrì Hámónì tí ó ṣàn sórí òkè Síónì: nítorí níbẹ̀ ni Olúwa gbé pàṣẹ ìbùkún, àní ìyè láé láé.”—Orin Dáfídì 133:1-3.

  • Ìdílé Jèhófà Ń Gbádùn Ìṣọ̀kan Ṣíṣeyebíye
    Ilé-Ìṣọ́nà—1996 | July 15
    • 6, 7. Báwo ni ìṣọ̀kan Ísírẹ́lì ṣe dà bí ìrì Òke Hámónì, ibo sì ni a ti lè rí ìbùkún Ọlọ́run lónìí?

      6 Báwo ni wíwà pa pọ̀ Ísírẹ́lì ní ìṣọ̀kan ṣe dà bí ìrì Òke Hámónì? Tóò, níwọ̀n bí ṣóńṣó òkè yìí ti fi 2,800 mítà ga ju ìtẹ́pẹrẹsẹ òkun lọ, ó fẹ́rẹ̀ẹ́ jẹ́ jálẹ̀ ọdún ní òjò dídì fi máa ń bò ó. Orí Òke Hámónì olójò dídì ń mú kí kùrukùru òru tutù, tí ó sì ń tipa bẹ́ẹ̀ pèsè ìrì tí ó tó, tí ń mú kí ewébẹ̀ lè la ìgbà ẹ̀rùn gígùn já. Ìgbì atẹ́gùn tútù láti òkè Hámónì lè gbé irú kùrukùru bẹ́ẹ̀ títí dé ibi jíjìnnà réré bíi gúúsù agbègbè Jerúsálẹ́mù, níbi tí wọn yóò ti sẹ̀ bí ìrì. Nítorí náà, onísáàmù náà tọ̀nà láti sọ pé ‘bí ìrì Hámónì tí ń ṣàn sórí Òke Síónì.’ Ẹ wo irú ìránnilétí àtàtà ti agbára ìdarí títuni lára tí ń gbé ìṣọ̀kan ìdílé ti àwọn olùjọsìn Jèhófà lárugẹ tí èyí jẹ́!

      7 Sáájú dídá ìjọ Kristẹni sílẹ̀, Síónì, tàbí Jerúsálẹ́mù, ni ojúkò ìjọsìn tòótọ́. Nítorí náà, níbẹ̀ ni Ọlọ́run pàṣẹ kí ìbùkún náà wà. Níwọ̀n bí ó ti jẹ́ pé Orísun gbogbo ìbùkún wà ní ibi mímọ́ ní Jerúsálẹ́mù lọ́nà ìṣàpẹẹrẹ, ibẹ̀ ni ìbùkún yóò ti wá. Nítorí pé ìjọsìn tòótọ́ kò sinmi lórí ọ̀gangan kan pàtó mọ́, nítorí náà, a lè rí ìbùkún, ìfẹ́, àti ìṣọ̀kan àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run jákèjádò ilẹ̀ ayé lónìí. (Jòhánù 13:34, 35) Kí ni díẹ̀ nínú àwọn kókó abájọ tí ń gbé ìṣọ̀kan yìí lárugẹ?

Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́