-
“Máa Ní Inú Dídùn Kíkọyọyọ Nínú Jèhófà”Ilé Ìṣọ́—2003 | December 1
-
-
“Má Ṣe Ìlara”
3, 4. Gẹ́gẹ́ bó ṣe wà nínú Sáàmù 37:1, ìmọ̀ràn wo ni Dáfídì fúnni, kí sì nìdí tó fi bá a mu láti kọbi ara sí ìmọ̀ràn náà lóde òní?
3 “Àwọn àkókò lílekoko tí ó nira láti bá lò” là ń gbé yìí, ìwà ibi sì gbòde kan. À ń fojú ara wa rí i pé ọ̀rọ̀ àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù ń ṣẹ, èyí tó sọ pé: “Àwọn ènìyàn burúkú àti àwọn afàwọ̀rajà yóò máa tẹ̀ síwájú láti inú búburú sínú búburú jù, wọn yóò máa ṣini lọ́nà, a ó sì máa ṣi àwọn pẹ̀lú lọ́nà.” (2 Tímótì 3:1, 13) Téèyàn ò bá ṣọ́ra, àṣeyọrí àti aásìkí tó dà bíi pé àwọn èèyàn burúkú ń ní á máa bani nínú jẹ́ ṣáá ni! Gbogbo ìyẹn sì lè kó ìpínyà ọkàn bá wa, tá ò sì ní lè máa fi ojú tẹ̀mí wo àwọn nǹkan bó ṣe yẹ mọ́. Wo bí ọ̀rọ̀ tó bẹ̀rẹ̀ Sáàmù kẹtàdínlógójì ṣe kìlọ̀ fún wa nípa ewu yìí, pé: “Má ṣe gbaná jẹ nítorí àwọn aṣebi. Má ṣe ìlara àwọn tí ń ṣe àìṣòdodo.”
4 Ojoojúmọ́ letí wa ń kún fún ìròyìn tá à ń gbọ́ lórí rédíò àti tẹlifíṣọ̀n àtèyí tó ń wá látinú ìwé ìròyìn, tó ń sọ nípa ìwà ìrẹ́jẹ àti àìsí ìdájọ́ òdodo. Àwọn oníṣòwò ń lu jìbìtì wọ́n sì ń mú un jẹ. Àwọn ọ̀daràn ń fojú àwọn ẹni ẹlẹ́ni gbolẹ̀ bó ṣe wù wọ́n. Àwọn apààyàn ń ṣe é gbé, a kì í rí wọn mú tàbí tá a bá rí wọn mú ká má fìyà jẹ wọ́n. Gbogbo irú ìwà àìsí ìdájọ́ òdodo báwọ̀nyí lè máa múnú bíni, kó sì máa bani lọ́kàn jẹ́. Bó ṣe dà bíi pé nǹkan ń ṣẹnuure fáwọn aṣebi tiẹ̀ lè múni bẹ̀rẹ̀ sí bínú wọn. Ṣùgbọ́n ṣé ìkanra wa yóò mú àwọn nǹkan sàn sí i? Ṣé ìbínú nítorí bó ṣe dà bíi pé àwọn aṣebi ń rọ́wọ́ mú yóò wá yí àtúbọ̀tán wọn padà? Rárá o! Kò sídìí fún wa láti yọ ara wa lẹ́nu, pé à ń “gbaná jẹ.” Kí nìdí tá a fi sọ bẹ́ẹ̀?
-
-
“Máa Ní Inú Dídùn Kíkọyọyọ Nínú Jèhófà”Ilé Ìṣọ́—2003 | December 1
-
-
6. Ẹ̀kọ́ wo la lè rí kọ́ látinú Sáàmù 37:1, 2?
6 Ǹjẹ́ ó wá yẹ ká máa bọkàn jẹ́ nítorí ọlà àwọn aṣebi tí kì í wà pẹ́ títí? Ẹ̀kọ́ tí Sáàmù kẹtàdínlógójì, ẹsẹ kìíní àti ìkejì ń kọ́ wa ni pé: Má ṣe jẹ́ kí àṣeyọrí wọn mú ọ yà kúrò nínú ipa ọ̀nà ìjọsìn Jèhófà tó o ti yàn. Kàkà bẹ́ẹ̀, ńṣe ni kó o gbájú mọ́ èrè àti góńgó tẹ̀mí tó ò ń lépa.—Òwe 23:17.
-