-
Ní Ìgbẹ́kẹ̀lé Pé Jehofa Yóò Mú Ète Rẹ̀ ṢẹIlé-Ìṣọ́nà—1994 | March 15
-
-
15. Báwo ni Dafidi ṣe sọ̀rọ̀jáde nípa ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀ nínú ìlérí Jehofa?
15 Ní nǹkan bí ọ̀rúndún mẹ́fà lẹ́yìn Jobu àti ní nǹkan bí ẹgbẹ̀rún ọdún ṣáájú kí Jesu tó wá sórí ilẹ̀-ayé, Dafidi sọ̀rọ̀jáde nípa ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀ nínú ayé titun kan. Ó sọ nínú àwọn psalmu pé: “Àwọn tí ó dúró de Oluwa ní yóò jogún ayé. Nítorí pé nígbà díẹ̀, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí . . . Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ayé; wọn ó sì máa ṣe inúdídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà. Olódodo ni yóò jogún ayé, yóò sì máa gbé inú rẹ̀ láéláé.” Nítorí ìgbàgbọ́ aláìyẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi rọni pé: “Gbẹ́kẹ̀lé Oluwa . . . Ṣe inúdídùn sí Oluwa pẹ̀lú, òun ó sì fi ìfẹ́-inú rẹ fún ọ.”—Orin Dafidi 37:3, 4, 9-11, 29.
-
-
Ní Ìgbẹ́kẹ̀lé Pé Jehofa Yóò Mú Ète Rẹ̀ ṢẹIlé-Ìṣọ́nà—1994 | March 15
-
-
22. Èéṣe tí a fi níláti fi ìgbẹ́kẹ̀lé wa sínú Jehofa?
22 Nínú ayé titun náà, aráyé olùṣòtítọ́ yóò rí ìmúṣẹ Romu 8:21 pé: “A ó sọ ẹ̀dá tìkaláraarẹ̀ di òmìnira kúrò nínú ẹrú ìdíbàjẹ́, sí òmìnira ògo àwọn ọmọ Ọlọrun.” Wọn yóò rí i tí àdúrà tí Jesu kọ́ àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ yóò ní ìmúṣẹ: “Kí ìjọba rẹ dé; ìfẹ́ tìrẹ ni kí a ṣe, bíi ti ọ̀run, bẹ́ẹ̀ ni ní ayé.” (Matteu 6:10) Nítorí náà, fi ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ kíkún sínú Jehofa nítorí pé ìlérí rẹ̀ tí kò lè ní àṣìṣe nínú ni pé: “Olódodo ni yóò jogún ayé, yóò sì máa gbé inú rẹ̀ láéláé.”—Orin Dafidi 37:29.
-